عن المِقدام بن معدي كرب رضي الله عنه عن النبي صلى الله عليه وسلم قال:
«إِذَا أَحَبَّ الرَّجُلُ أَخَاهُ فَلْيُخْبِرْهُ أَنَّهُ يُحِبُّهُ».

[صحيح] - [رواه أبو داود والترمذي والنسائي في الكبرى وأحمد] - [سنن أبي داود: 5124]
المزيــد ...

Lati ọdọ Al-Miqdam ọmọ Maadi Karib, ki Ọlọhun yọnu si i, o gba a wa lati ọdọ Anabi, ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a, o sọ pe:
“Bí ọkùnrin kan bá nífẹ̀ẹ́ arákùnrin rẹ̀, kí ó sọ fún un pé òun nífẹ̀ẹ́ rẹ̀”.

[O ni alaafia] - [Abu Daud ati Tirmiziy ati Nasaa'iy ni wọn gba a wa nínú al-Kubrọ, ati Ahmad] - [Sunanu ti Abu Daud - 5124]

Àlàyé

Anabi, ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a, n ṣe alaye ọkan lara awọn okunfa ti o lè fun ajọṣepọ ati ifẹ lagbara laarin awọn onigbagbọ ododo, òun naa ni pe ti ẹnikẹni ba nífẹ̀ẹ́ arakunrin rẹ̀, ki o sọ fun un pe oun nífẹ̀ẹ́ rẹ̀.

Lára àwọn àǹfààní hadiisi naa

  1. Ọla ti n bẹ fún ifẹ tó mọ́ kangá fun Ọlọhun Ọba Aleke ọla, tí kìí ṣe ifẹ nitori anfaani aye.
  2. A fẹ ki a maa sọ fún ẹniti a nifẹẹ nitori Ọlọhun pé a nifẹẹ rẹ̀, kí ifẹ ati irẹpọ le maa lekun si.
  3. Ìtànkálẹ̀ ifẹ laarin awọn onigbagbọ ododo maa n fún ìjẹ́ ọmọ iya ninu ẹsin lagbara ni, ó sì maa n dáàbò bo awujọ kuro nibi tútúká ati pinpin yẹlẹyẹlẹ.
Ṣíṣe àfihàn àwọn ìtumọ̀ sí èdè mìíràn
Èdè: Èdè Gẹ̀ẹ́sì Èdè Urdu Èdè Sípéènì Àlékún (67)