+ -

عن أبي هريرة رضي الله عنه أن رسول الله صلى الله عليه وسلم قال:
«أَتَدْرُونَ مَا الْغِيبَةُ؟»، قَالُوا: اللهُ وَرَسُولُهُ أَعْلَمُ، قَالَ: «ذِكْرُكَ أَخَاكَ بِمَا يَكْرَهُ»، قِيلَ: أَفَرَأَيْتَ إِنْ كَانَ فِي أَخِي مَا أَقُولُ؟ قَالَ: «إِنْ كَانَ فِيهِ مَا تَقُولُ فَقَدِ اغْتَبْتَهُ، وَإِنْ لَمْ يَكُنْ فِيهِ فَقَدْ بَهَتَّهُ».

[صحيح] - [رواه مسلم]
المزيــد ...

Láti ọ̀dọ̀ Abu Huraira- ki Ọlọhun yọnu si i- pe ojiṣẹ Ọlọhun- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- sọ pé:
"c2">“Njẹ ẹ mọ ohun ti n jẹ ọ̀rọ̀-ẹ̀yìn?”, wọn sọ pé: Ọlọhun ati ojiṣẹ Rẹ ni wọn ni imọ ju, o sọ pé: "c2">“Oun naa ni ki o maa sọ nipa ọmọ-ìyá rẹ ohun ti o korira”
, wọn sọ pé: Ti ohun ti mo n sọ ba n bẹ lara ọmọ-ìyá mi ńkọ́? O sọ pe: "c2">“Ti ohun ti o n sọ ba n bẹ lara ọmọ-iya rẹ, o ti sọ ọrọ rẹ lẹ́yìn nìyẹn, ṣùgbọ́n ti ko ba si lara rẹ, o ti dá àdápa irọ́ mọ ọn nìyẹn”.
O ni alaafia - Muslim gba a wa

Àlàyé

Anọbi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- n ṣàlàyé pàápàá ọ̀rọ̀-ẹ̀yìn ti o jẹ eewọ, oun naa ni: Sísọ nipa Mùsùlùmí ti ko si ni tòsí ohun ti o maa korira, bóyá o jẹ nibi awọn ìròyìn rẹ ti wọn dá mọ ọn tabi ti ìwà, gẹgẹ bii: Olojukan ẹlẹtan òpùrọ́, ati awọn nǹkan ti o jọ ọ ninu awọn ìròyìn ẹ̀gàn, kódà ki ìròyìn náà o wa lára rẹ.
Ṣùgbọ́n ti iroyin naa ko ba si lara rẹ, eyi tun buru ju ọ̀rọ̀-ẹ̀yìn lọ, oun ni BUHTAAN, itumọ rẹ ni: Adapa irọ mọ ọmọniyan pẹ̀lú nǹkan ti ko si lára rẹ.

Ìtumọ̀ sí èdè mìíràn: Èdè Gẹ̀ẹ́sì Èdè Urdu Èdè Sípéènì Èdè Indonéṣíà Èdè Uyghur Èdè Bangali Èdè Faransé Èdè Tọ́kì Èdè Rọ́ṣíà Èdè Bosnia Èdè Sinhala Èdè India Èdè Ṣáínà Èdè Páṣíà Èdè Vietnamese Èdè Tagalog Ti Kurdish Èdè Hausa Ti Pọtuga Malayalam Èdè Telgu Ti èdè Sawahili Tamil Burmese Thai Ede Jamani Ará Japan Pashto Assamese Ede Alibania Titi Sweden Ìtumọ̀ sí èdè Amharic Ìtumọ̀ sí èdè Dutch Titi èdè Gujarat Ti èdè Kyrgyz Ti èdè ìlú Nepal Ti èdè Lithuania Ti èdè Dari Ti èdè ìlú Serbia Ti èdè Somalia Ti èdè ìlú Tajikistan
Ṣíṣe àfihàn àwọn ìtumọ̀ sí èdè mìíràn

Lára àwọn àǹfààní hadiisi naa

  1. Didara ikọni ni ẹ̀kọ́ Anọbi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- bi o ṣe n ju àwọn ọ̀rọ̀ ẹ̀sìn silẹ nípasẹ̀ ìbéèrè.
  2. Didara ẹkọ àwọn saabe pẹ̀lú Anọbi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a-, nígbà tí wọ́n sọ pe: Ọlọhun ati ojiṣẹ Rẹ ni wọn mọ̀ julọ.
  3. Ki ẹni tí wọ́n ba bi ni ibeere nipa nǹkan ti kò mọ̀ sọ pe: Ọlọhun ni O ni imọ julọ.
  4. Sharia ṣọ àwùjọ pẹlu ṣiṣọ àwọn ẹ̀tọ́ àti ijẹ ọmọ-iya laarin wọn.
  5. Eewọ ni ọrọ-ẹyin ayafi ni àwọn iṣesi kan fun àǹfààní; ninu rẹ ni: Dida àbòsí padà, nibi ti ẹni tí wọ́n ṣe abosi si ti maa dárúkọ ẹni ti o ṣe abosi si i lọdọ ẹni ti o ba le ba a gba ẹtọ rẹ, o maa sọ pé: Lagbaja ṣe àbòsí fun mi, tabi o ṣe bayii fun mi, nínú rẹ̀ ni: Ìjíròrò nipa ọrọ ìgbéyàwó, tabi jijọ da nǹkan papọ, tabi mimu ilé ti ara ẹni, àti ohun ti o jọ ìyẹn.