عن خَولة الأنصاريةِ رضي الله عنها قالت: سمعت النبي صلى الله عليه وسلم يقول:
«إِنَّ رِجَالًا يَتَخَوَّضُونَ فِي مَالِ اللهِ بِغَيْرِ حَقٍّ، فَلَهُمُ النَّارُ يَوْمَ الْقِيَامَةِ».

[صحيح] - [رواه البخاري] - [صحيح البخاري: 3118]
المزيــد ...

Lati ọdọ Khaolah Al-Ansaariyyah- ki Ọlọhun yọnu si i- o sọ pé: Mo gbọ ti Anọbi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- n sọ pé:
“Dájúdájú àwọn èèyàn kan n wọ inu dúkìá Ọlọhun ni ọ̀nà tí kò tọ́, wọn maa wọ iná ni Ọjọ́ Àjíǹde”.

[O ni alaafia] - [Bukhaariy gba a wa] - [Sọhiihu ti Bukhaariy - 3118]

Àlàyé

Anọbi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- sọ nipa awọn eeyan kan ti wọn n ṣe ibajẹ ninu dúkìá àwọn Musulumi, ti wọn si n mu u ni ọ̀nà ti kò tọ́, eyi ni itumọ kan ti o kari nibi dukia, nibi kiko o jọ lati ibi ti ko ti ni ẹtọ, ati nina an sibi ti kii ṣe aaye rẹ ti o tọ, jíjẹ dúkìá àwọn ọmọ orukan maa wọ inú ẹ, àti awọn dúkìá ti a fi sọri awọn kan, ati titako agbafipamọ, ati mimu ninu dúkìá gbogbogboo ni ọ̀nà tí kò tọ́.
Lẹ́yìn náà ni Anọbi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- wa sọ pé ẹsan wọn ni iná ni Ọjọ́ Àjíǹde.

Lára àwọn àǹfààní hadiisi naa

  1. Dúkìá Ọlọhun ni dúkìá ti o wa ni ọwọ àwọn èèyàn, O fi wọn rólé nibẹ lati maa na an ní ọ̀nà tí ó bá òfin mu, ki wọn si jinna si ṣíṣe e kúmọkùmọ, èyí kárí gbogbo alaṣẹ ati awọn ti wọn yatọ si wọn ninu awọn èèyàn.
  2. Líle sharia níbi dúkìá gbogbogboo, ati pe ẹni ti o ba jẹ alaṣẹ lori nǹkan kan ninu ẹ, onítọ̀hún maa ṣe ìṣirò bi o ṣe gbà á ati bi o ṣe na an ni Ọjọ́ Àjíǹde.
  3. Ẹni tí ó n ṣe nnkan ti ko ba ofin mu ninu dúkìá naa maa ko sinu àdéhùn ìyà naa, bóyá o jẹ dúkìá rẹ ni tabi dúkìá ẹlòmíràn.
Ṣíṣe àfihàn àwọn ìtumọ̀ sí èdè mìíràn
Èdè: Èdè Gẹ̀ẹ́sì Èdè Urdu Èdè Sípéènì Àlékún (67)