عن أنس بن مالك رضي الله عنه قال: قال رسول الله صلى الله عليه وسلم:
«إِنَّ اللهَ لَيَرْضَى عَنِ الْعَبْدِ أَنْ يَأْكُلَ الْأَكْلَةَ فَيَحْمَدَهُ عَلَيْهَا، أَوْ يَشْرَبَ الشَّرْبَةَ فَيَحْمَدَهُ عَلَيْهَا».

[صحيح] - [رواه مسلم] - [صحيح مسلم: 2734]
المزيــد ...

Lati ọdọ Anas ọmọ Maalik- ki Ọlọhun yọnu si i- o sọ pe: Òjíṣẹ́ Ọlọhun- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- sọ pé:
“Dájúdájú Ọlọhun maa n yọnu si ẹrú ti o ba jẹun ti o wa dúpẹ́ lori rẹ, tabi ti o mu ti o wa dupẹ lórí rẹ”

[O ni alaafia] - [Muslim gba a wa] - [Sọhiihu ti Muslim - 2734]

Àlàyé

Anọbi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- n ṣàlàyé pe idupẹ ẹrú fun Olúwa rẹ lórí ọla Rẹ ati awọn idẹra Rẹ wa ninu awọn alamọri ti maa n fa iyọnu Ọlọhun; ti o ba jẹun, o maa sọ pé: ALHAMDULILLAAH, ti o ba mu, o maa sọ pé: ALHAMDULILLAAH.

Lára àwọn àǹfààní hadiisi naa

  1. Títa ọrẹ Ọlọhun ti O lágbára ti O gbọnngbọn, O fúnni ni arisiki, O si yọnu si idupẹ.
  2. Eeyan le ri iyọnu Ọlọhun ni ọ̀nà ti o rọrun jùlọ, gẹgẹ bii ṣíṣe ALHAMDULILLAAH lẹ́yìn jijẹ ati mimu.
  3. Ninu ẹkọ oúnjẹ ati nǹkan mimu ni: Idupẹ fun Ọlọhun lẹyin jijẹ ati mimu.
Ṣíṣe àfihàn àwọn ìtumọ̀ sí èdè mìíràn
Èdè: Èdè Gẹ̀ẹ́sì Èdè Urdu Èdè Sípéènì Àlékún (63)