عن ابن عباس رضي الله عنهما قال: قال رسول الله صلى الله عليه وسلم:
«من اقتبَسَ علْمًا مِنَ النُّجُومِ اقْتبَسَ شُعبَة مِن السِّحرِ، زادَ ما زادَ».

[صحيح] - [رواه أبو داود وابن ماجه وأحمد] - [سنن أبي داود: 3905]
المزيــد ...

Lati ọdọ ọmọ Abbaas- ki Ọlọhun yọnu si awọn mejeeji- o sọ pe: Òjíṣẹ́ Ọlọhun- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- sọ pé:
“Ẹni tí ó bá gba ìmọ̀ latara ìràwọ̀, onítọ̀hún ti gba ẹka kan ninu oògùn, bi o ba ṣe n lekun ninu imọ ìràwọ̀ naa ni kikọ oògùn rẹ naa ṣe maa lékún”.

[O ni alaafia] - [Abu Daud ati Ibnu Maajah ati Ahmad ni wọ́n gba a wa] - [Sunanu ti Abu Daud - 3905]

Àlàyé

Anọbi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- n ṣàlàyé pe ẹni ti o ba kọ́ imọ ìràwọ̀, ati fifi lílọ-bíbọ̀ rẹ, ati ìwọlé rẹ, ati ìjáde rẹ ṣe itọka si awọn ìṣẹ̀lẹ̀ orí ilẹ̀, bii ikú lagbaja, tabi iṣẹmi rẹ, tàbí àìsàn rẹ, ati nǹkan ti o jọ ìyẹn ninu nnkan ti o maa ṣẹlẹ̀ ni ọjọ́ iwájú, onítọ̀hún ti kọ́ ẹ̀yà kan ninu oògùn, bi èèyàn ba ṣe n kọ́ ọ sí naa ni yoo ṣe maa pọ̀ ni oògùn sí.

Lára àwọn àǹfààní hadiisi naa

  1. Ṣíṣe wiwo ìràwọ̀ ni eewọ, oun naa ni sísọ nípa ọjọ́ ọ̀la pẹ̀lú igbarale àwọn iṣesi ìràwọ̀; torí pé o wa nínú pípe apemọra ìní-ìmọ̀ kọ̀kọ̀.
  2. Wiwo ìràwọ̀ ti o jẹ eewọ wa ninu iran oògùn ti o tako ìmú-Ọlọ́hun-lọ́kan, yatọ si wiwo ìràwọ̀ láti mọ ibudojukọ, tabi ìwọlé àwọn àsìkò ati awọn oṣù, nǹkan ti o tọ́ ni.
  3. Bi o ba ṣe n kọ́ imọ wiwo ìràwọ̀ naa ni o ṣe maa lékún ni kíkọ́ imọ ẹka oògùn.
  4. Irawọ ni anfaani mẹta ti Ọlọhun sọ ninu tira Rẹ: Ọ̀ṣọ́ ni fun sánmọ̀, àmì ni ti a fi n mọ̀nà, ati nǹkan ti a maa n jù mọ́ àwọn èṣù.
Ṣíṣe àfihàn àwọn ìtumọ̀ sí èdè mìíràn
Èdè: Èdè Gẹ̀ẹ́sì Èdè Urdu Èdè Sípéènì Àlékún (63)