عن أبي هريرة رضي الله عنه أن رسول الله صلى الله عليه وسلم قال:
«مَنْ قَالَ: سُبْحَانَ اللهِ وَبِحَمْدِهِ، فِي يَوْمٍ مِائَةَ مَرَّةٍ، حُطَّتْ خَطَايَاهُ وَإِنْ كَانَتْ مِثْلَ زَبَدِ الْبَحْرِ».

[صحيح] - [متفق عليه] - [صحيح البخاري: 6405]
المزيــد ...

Lati ọdọ Abu Huraira- ki Ọlọhun yọnu si i- pe ojiṣẹ Ọlọhun- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- sọ pé:
“Ẹni ti o ba sọ pe: SUBHAANALLOOHI WA BIHAMDIHII, ni ìgbà ọgọ́rùn-ún ni ojúmọ́, wọn maa pa àwọn ẹṣẹ rẹ rẹ kódà ki o da gẹgẹ bii ìfòfó agbami odò”.

[O ni alaafia] - [Ohun ti wọ́n fi ẹnu kò lé lórí ni] - [Sọhiihu ti Bukhaariy - 6405]

Àlàyé

Anọbi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- n sọ pé ẹni tí o ba sọ pe SUBHAANALLOOHI WA BIHAMDIHII, ni ìgbà ọgọ́rùn-ún ni ojúmọ́, wọn maa pa ẹṣẹ rẹ rẹ, wọn si maa fi ori jin in, kódà ki ẹṣẹ rẹ pọ bii ifofo funfun ti o maa n wa lókè agbami odò nigba ti ìgbì rẹ ba n bì ati ti o ba ru sókè

Lára àwọn àǹfààní hadiisi naa

  1. Ẹsan yii maa jẹ ti ẹni tí ó bá wí i ni ojúmọ́ léraléra tabi kélekèle.
  2. AT-TESBIIH: Oun ni mimọ Ọlọhun kúrò nibi adinku, AL-HAMDU: Oun ni fifi pípé ròyìn rẹ pẹ̀lú ìfẹ́ ati gbigbetobi.
  3. Ohun ti a gbèrò nibi hadiisi naa ni pipa àwọn ẹṣẹ kéékèèké rẹ, ṣùgbọ́n ẹṣẹ ńlá, dandan ni ki èèyàn tuuba kuro nibẹ.
Ṣíṣe àfihàn àwọn ìtumọ̀ sí èdè mìíràn
Èdè: Èdè Gẹ̀ẹ́sì Èdè Urdu Èdè Sípéènì Àlékún (64)