+ -

عَنْ زِيَادِ بْنِ لَبِيدٍ رضي الله عنه قَالَ:
ذَكَرَ النَّبِيُّ صَلَّى اللَّهُ عَلَيْهِ وَسَلَّمَ شَيْئًا، فَقَالَ: «ذَاكَ عِنْدَ أَوَانِ ذَهَابِ الْعِلْمِ» قُلْتُ: يَا رَسُولَ اللَّهِ، وَكَيْفَ يَذْهَبُ الْعِلْمُ، وَنَحْنُ نَقْرَأُ الْقُرْآنَ وَنُقْرِئُهُ أَبْنَاءَنَا وَيُقْرِئُهُ أَبْنَاؤُنَا أَبْنَاءَهُمْ إِلَى يَوْمِ الْقِيَامَةِ؟ قَالَ: «ثَكِلَتْكَ أُمُّكَ زِيَادُ، إِنْ كُنْتُ لَأُرَاكَ مِنْ أَفْقَهِ رَجُلٍ بِالْمَدِينَةِ، أَوَلَيْسَ هَذِهِ الْيَهُودُ وَالنَّصَارَى يَقْرَؤونَ التَّوْرَاةَ وَالْإِنْجِيلَ، لَا يَعْمَلُونَ بِشَيْءٍ مِمَّا فِيهِمَا؟!».

[صحيح لغيره] - [رواه ابن ماجه]
المزيــد ...

Láti ọ̀dọ̀ Ziyaad ọmọ Labiid- ki Ọlọhun yọnu si i- o sọ pe:
Anọbi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- dárúkọ nǹkan kan, o wa sọ pé: "c2">“Ìyẹn nigba ti imọ bá lọ”, mo sọ pé: Irẹ ojiṣẹ Ọlọhun, bawo ni imọ ṣe máa lọ ti a si n ka Kuraani, ti a si n mu awọn ọmọ wa ka a, ti àwọn ọmọ wa naa si n mu awọn ọmọ wọn ka a titi di ọjọ igbende? O sọ pe: "c2">“Ó ṣe fún ẹ, irẹ Ziyaad, ti mo si n lérò pé ó wa ninu awọn ti wọn ni agbọye ẹsin ju ninu ilu Mẹdina, ṣe àwọn Júù ati awọn Kristẹni o maa ka Taoreeta ati Injiila ni, ti wọn kò sì ṣiṣẹ pẹlu nǹkan kan ninu nǹkan ti o wa nínú méjèèjì?!”
.
O ni alaafia fun nnkan ti o yàtọ̀ si i - Ibnu Maajah ni o gba a wa

Àlàyé

Anọbi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- jókòó laarin awọn saabe rẹ, o wa sọ pé: Eyi ni àsìkò ti wọn maa ká imọ kúrò lọ́dọ̀ àwọn èèyàn, Ziyaad ọmọ Labiid Al-Ansọọriy wá ṣe eemọ- ki Ọlọhun yọnu si i- o wa beere lọwọ Anọbi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a-, O wa sọ pé: Báwo ni wọ́n ṣe maa ká imọ kúrò lọ́dọ̀ wa?! Ti a si ti ka Kuraani ti a si ha a; mo fi Ọlọhun búra, a o maa ka a, a si maa jẹ ki awọn ìyàwó ati awọn ọmọ wa ka a, ati awọn ọmọ-ọmọ wa, Anọbi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- sọ ni ẹni tí n ṣe eemọ pé: O ṣe fun ẹ, irẹ Ziyaad! Tí mo si n ka ọ kun ara àwọn onimimọ nínú àwọn ará ilu Mẹdina! Lẹ́yìn naa ni Anọbi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- wa ṣàlàyé fun un pé: Pipadanu imọ kii ṣe pẹ̀lú pipadanu Kuraani; ṣùgbọ́n pipadanu imọ ni ki èèyàn má lò ó, Taoreeta ati Injiila n bẹ lọdọ awọn Juu ati awọn Kristẹni, tòun ti bẹ́ẹ̀ ko ṣe wọn ni anfaani, wọn ko si ṣe àǹfààní latara erongba àwọn méjèèjì; òun naa ni ki wọn lo ohun ti wọn mọ̀.

Ìtumọ̀ sí èdè mìíràn: Èdè Gẹ̀ẹ́sì Èdè Urdu Èdè Sípéènì Èdè Indonéṣíà Èdè Uyghur Èdè Bangali Èdè Tọ́kì Èdè Bosnia Èdè Sinhala Èdè India Èdè Vietnamese Èdè Hausa Malayalam Èdè Telgu Ti èdè Sawahili Burmese Thai Pashto Assamese Ede Alibania Titi Sweden Ìtumọ̀ sí èdè Amharic Ìtumọ̀ sí èdè Dutch Titi èdè Gujarat Ti èdè Kyrgyz Ti èdè ìlú Nepal Ti èdè Lithuania Ti èdè Dari Ti èdè ìlú Serbia Ti èdè Somalia Ti èdè ìlú Tajikistan
Ṣíṣe àfihàn àwọn ìtumọ̀ sí èdè mìíràn

Lára àwọn àǹfààní hadiisi naa

  1. Bibẹ Kuraani ati awọn tira ni iwájú àwọn èèyàn ko lee ṣe àǹfààní lai fi ṣe iṣẹ́ ṣe.
  2. Kíká imọ kúrò nilẹ maa wáyé pẹ̀lú àwọn àlámọ̀rí kan, nínú wọn ni: Ikú Anọbi (ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a), ati ikú àwọn onimimọ, ati ki èèyàn má lo imọ naa.
  3. Ninu awọn àmì ti ayé ba fẹ parẹ ni lílọ imọ ati ki èèyàn má lò ó.
  4. Ṣisẹnilojukokoro lórí lílo imọ; torí pé oun gan ni nǹkan ti a gbà lérò.