عن بريدة بن الحصيب رضي الله عنه أنه قال:
بَكِّرُوا بِصَلَاةِ الْعَصْرِ، فَإِنَّ النَّبِيَّ صَلَّى اللهُ عَلَيْهِ وَسَلَّمَ قَالَ: «مَنْ تَرَكَ صَلَاةَ الْعَصْرِ فَقَدْ حَبِطَ عَمَلُهُ».

[صحيح] - [رواه البخاري] - [صحيح البخاري: 553]
المزيــد ...

Lati ọdọ Buroida ọmọ Al-Husoib- ki Ọlọhun yọnu si i- o sọ pe:
Ẹ tete maa ki irun Asr, dajudaju Anabi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- sọ pé: “Ẹni ti o ba gbe irun Asr ju silẹ, dajudaju iṣẹ rẹ ti bajẹ”.

[O ni alaafia] - [Bukhaariy gba a wa] - [Sọhiihu ti Bukhaariy - 553]

Àlàyé

Anabi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- ṣe ikilọ kuro nibi ki èèyàn mọ̀ọ́mọ̀ lọ irun Asr lara tayọ asiko rẹ, ati pe ẹni ti o ba ṣe bẹẹ, iṣẹ rẹ ti bajẹ, o si ti lọ lasan.

Lára àwọn àǹfààní hadiisi naa

  1. Ṣisẹnilojukokoro lori ṣiṣọ irun Asr ni akọkọ asiko rẹ ati titete lọ ki i.
  2. Adehun iya ti o le koko fun ẹni ti o ba gbe irun Asr ju silẹ, ati pe ki èèyàn jẹ ki ó bọ́ ni asiko rẹ tobi ju ki eeyan jẹ ki irun mìíràn bọ́ lọ, oun ni irun aarin ti a ṣa lẹsa ni pato pẹlu aṣẹ ninu ọrọ Rẹ- Ọba ti ọla Rẹ ga-: (Ẹ ṣọ́ àwọn ìrun (wákàtí márààrún) àti (ní pàápàá jùlọ) ìrun ààrin). (Al-Baqarah: 238).
Ṣíṣe àfihàn àwọn ìtumọ̀ sí èdè mìíràn
Èdè: Èdè Gẹ̀ẹ́sì Èdè Urdu Èdè Sípéènì Àlékún (62)