عن عبد الله بن عمرو رضي الله عنهما أن النبي صلى الله عليه وسلم قال:
«بَلِّغُوا عَنِّي وَلَوْ آيَةً، وَحَدِّثُوا عَنْ بَنِي إِسْرَائِيلَ وَلَا حَرَجَ، وَمَنْ كَذَبَ عَلَيَّ مُتَعَمِّدًا فَلْيَتَبَوَّأْ مَقْعَدَهُ مِنَ النَّارِ».

[صحيح] - [رواه البخاري] - [صحيح البخاري: 3461]
المزيــد ...

Lati ọdọ Abdullah ọmọ ‘Amr - ki Ọlọhun yọnu si awọn mejeeji - ó ní dajudaju Anabi - ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a - sọ pé:
"Ẹ jẹ́ iṣẹ mi koda bo ṣe pẹlu aayah kan, kí ẹ sì sọrọ nipa àwọn ọmọ Ísírẹ́lì, kò sí aburu nibẹ, ṣugbọn ẹnikẹ́ni tí ó bá mọ̀ọ́mọ̀ parọ́ mọ́ mi, kí onitọhun yaa tètè mú ibùjókòó rẹ̀ nínú Iná".

[O ni alaafia] - [Bukhaariy gba a wa] - [Sọhiihu ti Bukhaariy - 3461]

Àlàyé

Anabi - ki ikẹ ati ọla Ọlohun maa ba a - n pàṣẹ pé ki a gbé ìmọ̀ oun kaakiri, yala o jẹ lati inu Al-Qur’an ni tabi lati inu Sunna, koda ki nkan naa jẹ kekere gẹgẹ bii aayah kan pere lati inu Al-Qur’an tabi Hadiisi kan pere, pẹlu majẹmu pé ki olujiṣẹ naa jẹ́ onimimọ nipa nkan ti ó fẹ́ jiṣẹ rẹ̀, tí ó sì fẹ́ kéde rẹ̀. Lẹyin naa ni Anabi- ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a- ṣalaye pé ko si aburu pẹlu sisọrọ nipa awọn ọmọ Ísírẹ́lì, ati nipa awọn ìsẹ̀lẹ̀ tí ó ṣẹlẹ̀ sí wọn, pẹlu pé kó ṣá ti má tako ofin sharia tiwa. Lẹyin naa, ó wá wa ní isọra kuro nibi píparọ́ mọ́ òun, nitori pé ẹnikẹni tí ó bá mọ̀ọ́mọ̀ parọ mọ oun, kí ó yaa tètè gba aaye kalẹ̀ fun ara rẹ̀ ninu ina.

Lára àwọn àǹfààní hadiisi naa

  1. Ìgbani níyànjú lati maa kéde òfin sharia Ọlọ́hun, àti pé ènìyàn gbọ́dọ̀ kéde ohun tí ó bá há sórí, tí ó sì gbágbọ̀yéé rẹ̀, koda bó jẹ́ pé díẹ̀ ni.
  2. Ọ̀ranyàn ni wíwá ìmọ̀ ofin sharia; kí a lè jọsin fun Ọlọhun ní ìrọ̀rùn, kí a sì lè kede sharia Rẹ̀ ní àwòrán tó lalaafia.
  3. Ọ̀ranyàn ni kí a ri i dájú pé èyíkéyìí hadiisi ní alaafia siwaju kí a tó kede rẹ̀, nitori kí a má baa kó sí inu ìlérí tó lekoko yii.
  4. Ìgbani níyanju lati maa sọ ododo ati ìmáa ṣọra nibi ọrọ sisọ, kí a má baa kó sinu irọ́, paapaa julọ ninu ofin Ọlọhun Ọba.
Ṣíṣe àfihàn àwọn ìtumọ̀ sí èdè mìíràn
Èdè: Èdè Gẹ̀ẹ́sì Èdè Urdu Èdè Sípéènì Àlékún (67)