+ -

عن ابن عباس رضي الله عنهما قال:
جاءَ رجُلُ إلى النبي صلى الله عليه وسلم فقال: يا رسولَ اللهِ، إن أحدنا يجدُ في نفسِهِ -يُعرِّضُ بالشَّيءِ- لأَن يكونَ حُمَمَةً أحَبُّ إليه من أن يتكلَّم بِهِ، فقال: «اللهُ أكبرُ، اللهُ أكبرُ، الحمدُ لله الذي ردَّ كيدَه إلى الوسوسَةِ».

[صحيح] - [رواه أبو داود والنسائي في الكبرى]
المزيــد ...

Lati ọdọ Ibnu Abbas- ki Ọlọhun yọnu si awọn mejeeji- o sọ pe:
Arakunrin kan wa ba Anọbi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- o sọ pe: Irẹ Òjíṣẹ́ Ọlọhun, dajudaju ọ̀kan ninu wa n ri ninu ẹ̀mí rẹ- o n pẹ́ nǹkan náà sọ pẹ̀lú itọka- o nífẹ̀ẹ́ si ki oun jẹ eeru ju ki o sọ ọ lọ, o wa sọ pe: “ Ọlọhun tobi Ọlọhun tobi, ọpẹ ni fun Ọlọhun ti O da ete rẹ pada si royiroyi".

O ni alaafia - Abu Daud ni o gba a wa

Àlàyé

Arakunrin kan wa sọdọ Anabi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- o sọ pe: Irẹ Ojisẹ Ọlọhun, dajudaju ẹnikan ninu wa n ri alamọri kan ninu ẹ̀mí rẹ ti o wa sínú ẹ̀mí, ṣùgbọ́n o tobi láti sọ ọ jáde, débi pe o nífẹ̀ẹ́ ki oun jẹ eeru ju ki o sọ ọ jade lọ, Bayii ni ojiṣẹ Ọlọhun- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- gbe Ọlọhun tobi ni ẹẹmeji, o si dupẹ fun Ọlọhun pe O da ete èṣù pada si royiroyi lasan.

Ìtumọ̀ sí èdè mìíràn: Èdè Gẹ̀ẹ́sì Èdè Urdu Èdè Sípéènì Èdè Indonéṣíà Èdè Uyghur Èdè Bangali Èdè Tọ́kì Èdè Bosnia Èdè Sinhala Èdè India Èdè Vietnamese Èdè Hausa Malayalam Èdè Telgu Ti èdè Sawahili Burmese Thai Pashto Assamese Ede Alibania Titi Sweden Ìtumọ̀ sí èdè Amharic Ìtumọ̀ sí èdè Dutch Titi èdè Gujarat Ti èdè Kyrgyz Ti èdè ìlú Nepal Ti èdè Lithuania Ti èdè Dari Ti èdè ìlú Serbia Ti èdè Somalia Ti èdè ìlú Tajikistan Ti èdè Rwanda
Ṣíṣe àfihàn àwọn ìtumọ̀ sí èdè mìíràn

Lára àwọn àǹfààní hadiisi naa

  1. Alaye pe èṣù maa n retí ìkángun olugbagbọ pẹlu royiroyi; ki o le da wọn pada lati inu igbagbọ lọ si inu aigbagbọ.
  2. Alaye lilẹ èṣù pẹlu awọn oni igbagbọ nigba ti ko lee ni ikapa afi lori royiroyi.
  3. O tọ́ fun olugbagbọ ki o ṣẹri kuro nibi awọn royiroyi èṣù, ki o si ti i dànù.
  4. Ṣíṣe lofin gbigbe Ọlọhun tobi nibi nnkan ti a fẹ tabi eemọ latari nnkan tabi nnkan ti o jọ ọ ninu awọn alamọri.
  5. Ṣíṣe lofin ṣíṣe ibeere Musulumi lọdọ onimimọ nipa gbogbo nnkan ti o ba ru u loju.