+ -

عَنْ عَائِشَةَ أُمِّ المؤمنين رضي الله عنها:
أَنَّ أُمَّ سَلَمَةَ ذَكَرَتْ لِرَسُولِ اللهِ صَلَّى اللهُ عَلَيْهِ وَسَلَّمَ كَنِيسَةً رَأَتْهَا بِأَرْضِ الْحَبَشَةِ، يُقَالُ لَهَا مَارِيَةُ، فَذَكَرَتْ لَهُ مَا رَأَتْ فِيهَا مِنَ الصُّوَرِ، فَقَالَ رَسُولُ اللهِ صَلَّى اللهُ عَلَيْهِ وَسَلَّمَ: «أُولَئِكَ قَوْمٌ إِذَا مَاتَ فِيهِمُ الْعَبْدُ الصَّالِحُ، أَوِ الرَّجُلُ الصَّالِحُ، بَنَوْا عَلَى قَبْرِهِ مَسْجِدًا، وَصَوَّرُوا فِيهِ تِلْكَ الصُّوَرَ، أُولَئِكَ شِرَارُ الْخَلْقِ عِنْدَ اللهِ».

[صحيح] - [متفق عليه]
المزيــد ...

Lati ọdọ 'Aaisha iya awọn olugbagbọ- ki Ọlọhun yọnu si i-:
Dajudaju Ummu Salamah dárúkọ ṣọọṣi kan ti o ri ni ilẹ̀ Habasha fun ojiṣẹ Ọlọhun- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a-, wọn n pe e ni Maariyah, o wa sọ nnkan ti o ri nibẹ fun un ninu awọn aworan, ni ojiṣẹ Ọlọhun- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- wa sọ pe: "Awọn wọnyẹn ni ìjọ kan, ti ẹru rere ba ku ninu wọn tabi ọkùnrin rere, wọn maa kọ mọsalasi kan sori saare rẹ, wọn yoo si ya awọn aworan yẹn síbẹ̀, awọn wọnyẹn ni awọn ti wọn buru julọ ninu ẹda lọdọ Ọlọhun".

O ni alaafia - Ohun ti wọ́n fi ẹnu kò lé lórí ni

Àlàyé

Iya awọn olugbagbọ Ummu Salamah- ki Ọlọhun yọnu si i- sọ fun Anabi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- pe dajudaju nigba ti oun fi wa lori ilẹ Habasha, oun ri ṣọọṣi kan- wọn n pe e ni Maariyah- ti awọn aworan ati awọn ẹṣọ ati awọn fọto n bẹ nibẹ; ni ti ìyàlẹ́nu latara ìyẹn! Bayii ni Anabi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- ba ṣàlàyé awọn okunfa gbigbe awọn aworan yii síbẹ̀; O sọ pe: Dajudaju awọn ti o dárúkọ wọnyii ti ẹni rere ba ku laaarin wọn, wọn maa kọ mọsalasi kan sori saare rẹ ti wọn ma maa kirun nibẹ, ti wọn si maa ya awọn aworan yẹn, O ṣàlàyé pe dajudaju ẹni ti o ba ṣe yẹn jẹ ẹni ti o buru julọ ninu ẹda lọdọ Ọlọhun- ti ọla Rẹ ga-; nitori pe iṣe rẹ maa ja si dida orogun pọ mọ Ọlọhun- ti ọla Rẹ ga-.

Ìtumọ̀ sí èdè mìíràn: Èdè Gẹ̀ẹ́sì Èdè Urdu Èdè Sípéènì Èdè Indonéṣíà Èdè Uyghur Èdè Bangali Èdè Faransé Èdè Tọ́kì Èdè Rọ́ṣíà Èdè Bosnia Èdè Sinhala Èdè India Èdè Ṣáínà Èdè Páṣíà Èdè Vietnamese Èdè Tagalog Ti Kurdish Èdè Hausa Ti Pọtuga Malayalam Èdè Telgu Ti èdè Sawahili Tamil Burmese Thai Ará Japan Pashto Assamese Ede Alibania Titi Sweden Ìtumọ̀ sí èdè Amharic Titi èdè Gujarat Ti èdè Kyrgyz Ti èdè ìlú Nepal Ti èdè Dari Ti èdè Somalia Ti èdè Rwanda
Ṣíṣe àfihàn àwọn ìtumọ̀ sí èdè mìíràn

Lára àwọn àǹfààní hadiisi naa

  1. Ṣíṣe kikọ awọn mọsalasi lori awọn saare leewọ, tabi kiki irun nibẹ, tabi sisin awọn oku si awọn mọsalasi; lati dina mọ okunfa ẹbọ ṣíṣe.
  2. Kikọ awọn mọsalasi lori awọn saare, ati gbigbe awọn aworan síbẹ̀, jẹ iṣẹ Juu ati Nasara, ati pe dajudaju ẹni ti o ba ṣe èyí, dajudaju o ti fi iwa jọ wọn.
  3. Ṣíṣe yiya aworan awọn nnkan ti wọn ni ẹmi leewọ.
  4. Ẹni ti o ba kọ mọsalasi kan lori saare ti o si ya awọn aworan síbẹ̀, o ti wa ninu ẹni ti o buru julọ ninu ẹda Ọlọhun- ti ọla Rẹ ga-.
  5. Idaabo bo Sharia fun agbegbe imu Ọlọhun ni Ọkan ṣoṣo jẹ idaabo bo kan ti o pe, pẹlu kikọdi gbogbo ọna ti o le ja si ẹbọ ṣiṣe.
  6. Kikọ kuro nibi aṣẹju nipa awọn ẹni rere; nitori pe o jẹ okunfa kiko sinu ẹbọ ṣíṣe.