+ -

عَنْ جَابِرِ بْنِ عَبْدِ اللَّهِ رضي الله عنهما أَنَّ النَّبِيَّ صَلَّى اللَّهُ عَلَيْهِ وَسَلَّمَ قَالَ:
«لَا تَعَلَّمُوا الْعِلْمَ لِتُبَاهُوا بِهِ الْعُلَمَاءَ، وَلَا لِتُمَارُوا بِهِ السُّفَهَاءَ، وَلَا تَخَيَّرُوا بِهِ الْمَجَالِسَ، فَمَنْ فَعَلَ ذَلِكَ، فَالنَّارُ النَّارُ».

[صحيح] - [رواه ابن ماجه]
المزيــد ...

Láti ọ̀dọ̀ Jaabir ọmọ Abdullahi- ki Ọlọhun yọnu si àwọn mejeeji- pe Anọbi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- sọ pé:
"c2">“Ẹ ma kọ́ imọ lati le maa fi ba àwọn onimimọ ṣe iyanran, tabi lati le baa maa fi ja àwọn omugọ níyàn, ẹ si ma ṣẹsa lati wa ni iwájú ni àwọn àpéjọ pẹ̀lú ẹ, ẹni tí ó bá ṣe iyẹn, iná ni, iná ni”.

O ni alaafia - Ibnu Maajah ni o gba a wa

Àlàyé

Anọbi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- kilọ kúrò nibi wiwa imọ lati maa fi ba àwọn onimimọ ṣe iyanran, ati lati le fi hàn pé onimimọ bii tiyín ni èmi náà, tabi lati fi ba àwọn omugọ ati awọn ti làákàyè wọn lẹ sọ̀rọ̀ lati ba wọn jiyàn, tabi ki o kọ imọ lati wa ni iwájú ni àpéjọ, ti wọn si maa ti i saaju ẹlòmíràn nibẹ. Ẹni tí ó bá ṣe iyẹn; o ni ẹtọ si iná pẹlu ṣekarimi rẹ ati àìní imọkanga nibi wiwa imọ naa nítorí Ọlọhun.

Ìtumọ̀ sí èdè mìíràn: Èdè Gẹ̀ẹ́sì Èdè Urdu Èdè Sípéènì Èdè Indonéṣíà Èdè Uyghur Èdè Bangali Èdè Tọ́kì Èdè Bosnia Èdè Sinhala Èdè India Èdè Vietnamese Èdè Hausa Malayalam Èdè Telgu Ti èdè Sawahili Burmese Thai Pashto Assamese Ede Alibania Titi Sweden Ìtumọ̀ sí èdè Amharic Ìtumọ̀ sí èdè Dutch Titi èdè Gujarat Ti èdè Kyrgyz Ti èdè ìlú Nepal Ti èdè Lithuania Ti èdè Dari Ti èdè ìlú Serbia Ti èdè Somalia Ti èdè ìlú Tajikistan
Ṣíṣe àfihàn àwọn ìtumọ̀ sí èdè mìíràn

Lára àwọn àǹfààní hadiisi naa

  1. Àdéhùn ìyà iná fun ẹni ti o ba kọ imọ lati maa ṣe iyanran pẹ̀lú ẹ, tabi ìjiyàn pẹ̀lú ẹ, tabi wiwa ni iwájú nibi àpéjọ pẹ̀lú ẹ, ati bẹẹ bẹẹ lọ.
  2. Pataki mimọ àníyàn kangá fun ẹni ti o ba kọ́ imọ ti o si tun kọ ẹlòmíràn.
  3. Aniyan ni ipilẹ àwọn iṣẹ, ori rẹ naa si ni ẹsan maa wa.