+ -

عَنْ النَّوَّاسِ بْنِ سَمْعَانَ الْأَنْصَارِيِّ رضي الله عنه عَنْ رَسُولِ اللهِ صَلَّى اللهُ عَلَيْهِ وَسَلَّمَ قَالَ:
«ضَرَبَ اللهُ مَثَلًا صِرَاطًا مُسْتَقِيمًا، وَعَلَى جَنْبَتَيْ الصِّرَاطِ سُورَانِ، فِيهِمَا أَبْوَابٌ مُفَتَّحَةٌ، وَعَلَى الْأَبْوَابِ سُتُورٌ مُرْخَاةٌ، وَعَلَى بَابِ الصِّرَاطِ دَاعٍ يَقُولُ: أَيُّهَا النَّاسُ، ادْخُلُوا الصِّرَاطَ جَمِيعًا، وَلَا تَتَعَرَّجُوا، وَدَاعٍ يَدْعُو مِنْ فَوْقِ الصِّرَاطِ، فَإِذَا أَرَادَ يَفْتَحُ شَيْئًا مِنْ تِلْكَ الْأَبْوَابِ، قَالَ: وَيْحَكَ لَا تَفْتَحْهُ، فَإِنَّكَ إِنْ تَفْتَحْهُ تَلِجْهُ، وَالصِّرَاطُ الْإِسْلَامُ، وَالسُّورَانِ: حُدُودُ اللهِ، وَالْأَبْوَابُ الْمُفَتَّحَةُ: مَحَارِمُ اللهِ، وَذَلِكَ الدَّاعِي عَلَى رَأْسِ الصِّرَاطِ: كِتَابُ اللهِ، وَالدَّاعِي مِنِ فَوْقَ الصِّرَاطِ: وَاعِظُ اللهِ فِي قَلْبِ كُلِّ مُسْلِمٍ».

[صحيح] - [رواه الترمذي وأحمد]
المزيــد ...

Lati ọdọ An-Nawwaas ọmọ Sam’haan Al-Ansaariy- ki Ọlọhun yọnu si i- lati ọdọ ojiṣẹ Ọlọhun- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- o sọ pé:
"c2">“Ọlọhun fi àkàwé kan lélẹ̀ nipa ojú ọ̀nà tààrà kan, ti ògiri méjì wa ni ẹ̀gbẹ́ méjèèjì ojú ọ̀nà naa, ti àwọn ẹnu ọ̀nà ti wọn ṣí silẹ wa nibẹ, ti àwọn aṣọ ẹnu ọ̀nà ti wọn dà wálẹ̀ si n bẹ ni àwọn ẹnu ọ̀nà naa, olupepe kan n bẹ ni ẹnu ọ̀nà ojú ọ̀nà naa ti n sọ pé: Ẹ̀yin èèyàn, gbogbo yin ẹ ko sínú ọ̀nà naa, ẹ má ṣe wọ́, ati olupepe kan ti n pepe lati òkè ọ̀nà naa, ti o ba ti wa fẹ ṣí nǹkan kan ninu awọn ojú ọ̀nà yẹn, o maa sọ pé: Káì, ma ṣi i, ti o ba fi le ṣi i wàá wọ̀ ọ́, ojú ọ̀nà naa ni Isilaamu, àwọn ògiri méjèèjì naa ni: Awọn ààlà Ọlọhun, àwọn ẹnu ọ̀nà ti wọn ṣi silẹ ni: Awọn nǹkan ti Ọlọhun ṣe ni eewọ, ẹni tí n pepe ni orí ojú ọ̀nà naa ni: Tira Ọlọhun, ẹni tí n pepe ni òkè ojú ọ̀nà naa ni: Oníwàásù Ọlọhun ninu ọkàn gbogbo Musulumi”.

O ni alaafia - Tirmiziy ni o gba a wa

Àlàyé

Anọbi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- ṣàlàyé pe: Ọlọhun fi àkàwé lélẹ̀ fun Isilaamu pẹlu ojú ọ̀nà tààrà ti o tẹ́ ti kò wọ́, tí ògiri méjì n bẹ ni ẹ̀gbẹ́ méjèèjì ojú ọ̀nà naa ti wọn rọkirika rẹ, àwọn méjèèjì náà ni àwọn ààlà Ọlọhun, àwọn ẹnu ọ̀nà ti wọn ṣi silẹ n bẹ láàrin ògiri méjì yii, àwọn naa ni àwọn nǹkan ti Ọlọhun ṣe ni eewọ, àwọn aṣọ ẹnu ọ̀nà n bẹ ni àwọn ẹnu ọ̀nà naa ti ko nii jẹ ki ẹni tí n kọjá ri ẹni tí ó wà ninu rẹ, olupepe kan si n bẹ ni ìbẹ̀rẹ̀ ojú ọ̀nà naa ti n dari àwọn èèyàn ti o si n sọ fún wọn pé: Ẹ maa rìn lọ lori ẹ láì fi si etí ati ẹ̀gbẹ́, olupepe yii ni tira Ọlọhun, olupepe mìíràn tun wa ni òkè ọ̀nà naa; olupepe yii, gbogbo igba ti ẹni tí n rìn ni oju ọna naa ba ti fẹ ṣi aṣọ ẹnu ọ̀nà yẹn díẹ̀, o maa jagbe mọ́ ọn, o maa wa sọ fún un pé: Ó ṣe fún ẹ, o ò gbọdọ ṣí i! Ti o ba ṣi i, waa wọ inú ẹ, o ò si nii ni ikapa lati kọ̀ fun ara rẹ lati má wọlé, olupepe yii ni oníwàásù Ọlọhun ninu ọkan gbogbo Musulumi.

Ìtumọ̀ sí èdè mìíràn: Èdè Gẹ̀ẹ́sì Èdè Urdu Èdè Sípéènì Èdè Indonéṣíà Èdè Uyghur Èdè Bangali Èdè Tọ́kì Èdè Bosnia Èdè Sinhala Èdè India Èdè Vietnamese Èdè Hausa Malayalam Èdè Telgu Ti èdè Sawahili Burmese Thai Pashto Assamese Ede Alibania Titi Sweden Ìtumọ̀ sí èdè Amharic Ìtumọ̀ sí èdè Dutch Titi èdè Gujarat Ti èdè Kyrgyz Ti èdè ìlú Nepal Ti èdè Lithuania Ti èdè Dari Ti èdè ìlú Serbia Ti èdè Somalia Ti èdè ìlú Tajikistan
Ṣíṣe àfihàn àwọn ìtumọ̀ sí èdè mìíràn

Lára àwọn àǹfààní hadiisi naa

  1. Isilaamu ni ẹsin òdodo, oun si ni ọ̀nà tààrà ti o maa mu wa de alujanna.
  2. Dandan ni didunni mọ àwọn ààlà Ọlọhun ati nǹkan ti O ṣe ni ẹtọ ati nǹkan ti O ṣe ni eewọ, ati pe fífi ọwọ dẹngẹrẹ mu un maa fa ìparun.
  3. Ọla ti n bẹ fun Kuraani, ati ṣisẹnilojukokoro lori ṣíṣe àmúlò rẹ, imọna wa ninu rẹ ati imọlẹ ati jijẹ èrè.
  4. Aanu Ọlọhun si awọn ẹru Rẹ, ati si ohun ti O fi sinu ọkàn àwọn mumini ni ohun ti yoo kọ fun wọn ti o si maa ṣe iṣiti fun wọn ti wọn ko fi nii ko sinu ìparun.
  5. Ninu aanu Ọlọhun ni pe O fun awọn ẹru ni àwọn ìdènà ti ko nii jẹ ki wọn ko sinu ẹṣẹ.
  6. Ninu ọna ìkọ́ni ni ẹ̀kọ́ ni fifi àkàwé lélẹ̀ lati fi sun un mọ ati lati le ṣàlàyé.