عن عبد الله بن عمرو رضي الله عنهما عن النبي صلى الله عليه وسلم قال:
«مَنْ قَتَلَ مُعَاهَدًا ‌لَمْ ‌يَرَحْ ‌رَائِحَةَ الْجَنَّةِ، وَإِنَّ رِيحَهَا تُوجَدُ مِنْ مَسِيرَةِ أَرْبَعِينَ عَامًا».

[صحيح] - [رواه البخاري] - [صحيح البخاري: 3166]
المزيــد ...

Lati ọdọ Abdullahi ọmọ Amr- ki Ọlọhun yọnu si awọn mejeeji- lati ọdọ Anabi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- o sọ pe:
“Ẹni ti o ba pa ẹni a gba adehun lọwọ rẹ ko nii gbọ́ oorun alujanna, ati pe dajudaju oorun rẹ wọn maa n gbọ́ ọ lati ijinna ogoji ọdun”.

[O ni alaafia] - [Bukhaariy gba a wa] - [Sọhiihu ti Bukhaariy - 3166]

Àlàyé

Anabi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- n ṣàlàyé adehun iya ti o le koko to wa lori pe dajudaju ẹni ti o ba pa ẹni ti a gba adehun lọwọ rẹ- oun ni ẹni ti o wọ ilẹ̀ Isilaamu ninu awọn alaigbagbọ pẹlu adehun ati ifọkanbalẹ- pe ẹni naa ko nii gbọ́ oorun alujanna, ati pe dajudaju oorun rẹ maa jẹ ijiina irin ogoji ọdun.

Lára àwọn àǹfààní hadiisi naa

  1. Ṣíṣe leewọ pipa Al-Mu’aahad ati Adh-dhimmiyy ati Al-Mustahman ninu awọn alaigbagbọ, ati pe o jẹ ẹṣẹ nla ninu awọn ẹṣẹ ńláńlá.
  2. Al-Mu’aahad ni: Ẹni ti wọn gba adehun lọwọ rẹ ninu awọn alaigbagbọ ti o si n gbe ni ilu rẹ ti ko gbe ogun ti awọn Musulumi ti awọn naa ko gbe ogun ti i, Adh-dhimmiyy ni: Ẹni ti o sọ ilẹ̀ awọn Musulumi di ilu ti o si n san ìsákọ́lẹ̀, Al-Mustahman ni: Ẹni ti o wọ inu ilẹ̀ awọn Musulumi pẹlu adehun ati ifọkanbalẹ fun asiko kan pàtó.
  3. Ikilọ kuro nibi jijanba awọn adehun pẹlu awọn ti wọn ko kii ṣe Musulumi.
Ṣíṣe àfihàn àwọn ìtumọ̀ sí èdè mìíràn
Èdè: Èdè Gẹ̀ẹ́sì Èdè Urdu Èdè Sípéènì Àlékún (58)
Àlékún