عن أبي هريرة رضي الله عنه قال:
لَعَنَ رَسُولُ اللهِ صَلَّى اللهُ عَلَيْهِ وَسَلَّمَ الرَّاشِيَ وَالْمُرْتَشِيَ فِي الْحُكْمِ.

[صحيح] - [رواه الترمذي وأحمد] - [سنن الترمذي: 1336]
المزيــد ...

Lati ọdọ Abu Huraira, ki Ọlọhun yọnu si i, o sọ pe:
Ojiṣẹ Ọlọhun – ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a - ṣẹ́ ibi lé ẹni ti n san abẹtẹlẹ ati ẹni ti n gba a nibi idajọ (igbẹjọ).

[O ni alaafia] - [Tirmiziy ati Ahmad ni wọ́n gba a wa] - [Sunanu ti Tirmidhiy - 1336]

Àlàyé

Anabi – ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a - ṣẹ ibi ilejina si ikẹ Ọlọhun ti O biyi ti O gbọnngbọn le ẹni ti n san abẹtẹlẹ ati ẹni ti n gba a.
Ati pe ninu rẹ naa ni eyiti wọn maa n fun awọn adajọ lati le jẹ ki wọn o ṣe abosi nínú ẹjọ ti wọn n da; ki ẹni ti o fun un le baa de ibi nkan ti o n fẹ lai ni ẹtọ si i.

Lára àwọn àǹfààní hadiisi naa

  1. Sisan abẹtẹlẹ jẹ eewọ, ati gbigba a, ati ṣiṣe alagata nibẹ, ati ṣiṣe ikunlọwọ lori rẹ; latari nkan ti o wa ninu rẹ ni ikunlọwọ lori ibajẹ.
  2. Abẹtẹlẹ wa ninu awọn ẹṣẹ ti o tobi; torí pé dajudaju ojiṣẹ Ọlọhun – ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a - ṣẹbi le ẹni ti n gba a ati ẹni ti n san an.
  3. Ọran nla ni abẹtẹlẹ jẹ ni agbegbe idajọ ati ofin, ẹṣẹ ti o ni agbara si tun ni; latari nkan ti o wa ninu rẹ ni abosi ati ṣiṣe idajọ pẹlu nkan ti o yatọ si nkan ti Ọlọhun sọkalẹ.
Ṣíṣe àfihàn àwọn ìtumọ̀ sí èdè mìíràn
Èdè: Èdè Gẹ̀ẹ́sì Èdè Urdu Èdè Sípéènì Àlékún (59)
Àlékún