عَنْ مَحْمُودِ بْنِ لَبِيدٍ رضي الله عنه أَنَّ رَسُولَ اللَّهِ صَلَّى اللَّهُ عَلَيْهِ وَسَلَّمَ قَالَ:
«إِنَّ أَخْوَفَ مَا أَخَافُ عَلَيْكُمُ الشِّرْكُ الْأَصْغَرُ» قَالُوا: وَمَا الشِّرْكُ الْأَصْغَرُ يَا رَسُولَ اللهِ؟ قَالَ: «الرِّيَاءُ، يَقُولُ اللهُ عز وجل لَهُمْ يَوْمَ الْقِيَامَةِ إِذَا جُزِيَ النَّاسُ بِأَعْمَالِهِمْ: اذْهَبُوا إِلَى الَّذِينَ كُنْتُمْ تُرَاؤُونَ فِي الدُّنْيَا، فَانْظُرُوا هَلْ تَجِدُونَ عِنْدَهُمْ جَزَاءً؟».

[حسن] - [رواه أحمد] - [مسند أحمد: 23630]
المزيــد ...

Lati ọdọ Mahmud ọmọ Labiid- ki Ọlọhun yọnu si i- dajudaju ojiṣẹ Ọlọhun- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- sọ pé:
"Dajudaju nnkan ti mo n bẹru julọ nipa yin ni ẹbọ kekere" wọn sọ pe: Ki ni ẹbọ kekere irẹ ojiṣẹ Ọlọhun? O sọ pe: "Ṣekarimi ni, Ọlọhun- Alagbara ti O gbọnngbọn- maa sọ fun wọn ni ọjọ igbedide ti wọn ba ti san awọn eniyan lẹsan pẹlu awọn iṣẹ wọn pé: Ẹ lọ ba awọn ti ẹ maa n ṣe karimi fun ni aye, ki ẹ si wo boya ẹ maa ri ẹsan kankan lọdọ wọn?"

[O daa] - [Ahmad ni o gba a wa] - [Musnad ti Ahmad - 23630]

Àlàyé

Anabi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- n sọ pe dajudaju nnkan ti o pọ julọ ti oun n bẹru rẹ lori awọn ijọ rẹ ni: Ẹbọ kékeré, oun ni: Ṣekarimi; ki o maa ṣiṣẹ nitori awọn eniyan. Lẹyin naa o sọ nipa iya awọn oniṣekarimi ni ọjọ igbedide, pe wọn maa sọ fun wọn pé: Ẹ lọ ba awọn ẹni ti ẹ n ṣiṣẹ nitori wọn, ki ẹ si wo boya wọn kapa sisan yin lẹ́san ati fifun yin ni ẹsan lori iṣẹ yẹn?!

Lára àwọn àǹfààní hadiisi naa

  1. Jijẹ dandan mimọ iṣẹ kanga fun Ọlọhun- Alagbara ti O gbọnngbọn-, ati ikilọ kuro nibi ṣekarimi.
  2. Ile koko ini aanu rẹ- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- lori ìjọ rẹ ati iko akolekan rẹ lori imọna wọn ati ṣiṣe iṣiti rẹ fun wọn.
  3. Ti o ba ṣe pe ibẹru rẹ- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- nìyí, ti o si n ba awọn saabe sọ̀rọ̀, ti wọn si ṣe pe awọn ni aṣaaju awọn ẹni rere, a jẹ pe ibẹru rẹ lori awọn ti wọn wa lẹyin wọn lo le julọ.
Ṣíṣe àfihàn àwọn ìtumọ̀ sí èdè mìíràn
Èdè: Èdè Gẹ̀ẹ́sì Èdè Urdu Èdè Sípéènì Àlékún (56)