+ -

عَنْ أَبِي هُرَيْرَةَ رَضِيَ اللَّهُ عَنْهُ أَنَّ النَّبِيَّ صَلَّى اللهُ عَلَيْهِ وَسَلَّمَ قَالَ:
«مَا مِنْ يَوْمٍ يُصْبِحُ العِبَادُ فِيهِ إِلَّا مَلَكَانِ يَنْزِلاَنِ، فَيَقُولُ أَحَدُهُمَا: اللَّهُمَّ أَعْطِ مُنْفِقًا خَلَفًا، وَيَقُولُ الآخَرُ: اللَّهُمَّ أَعْطِ مُمْسِكًا تَلَفًا».

[صحيح] - [متفق عليه] - [صحيح البخاري: 1442]
المزيــد ...

Lati ọdọ Abu Hurayrah, kí Ọlọhun bá wa yọnu si, o sọ pe: dájúdájú Anọbi - ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ máa ba - sọ bayi pe:
Kosi ọjọ kan ti awọn ẹrusin yóò jí ní àárọ̀ ayaafi kí ó jasipe awọn malaika (iranṣẹ Ọlọhun) meji yoo sọkalẹ sí ọdọ ẹnikọọkan, ọkan ninu awọn mejeeji yóò máa ṣọ pe: "Irẹ Ọlọhun dakun bá mi ṣe iropo owo fún ẹni tí n nawo rẹ, bẹẹ ni ikeji yóò máa ṣọ pe: "Bami fi iparun ati ibajẹ sinu owo ẹni tí ó kọ̀ lati ma na owo, tí ó wowọ́ mọ́n owo kankan.

[O ni alaafia] - [Ohun ti wọ́n fi ẹnu kò lé lórí ni] - [Sọhiihu ti Bukhaariy - 1442]

Àlàyé

Anọbi (ki ikẹ Olohun ati ola Re máa bá) ti fún wa ni iro pe kosi ojo kan ti oorun yo tabi ayaafi ki awon malaika meji sokale ti won yóò sì máa pe Olohun, okan ninu won yóò sọ pé:
"Olohun bami fi ọpọ ropo fún ẹni tí n nawo rẹ ni itẹle aṣẹ Olohun, ati fún awon ebi (ọmọ, iyawo, baba, ati iya....) ati igbalejo, ati sí bí awon iṣẹ àṣegbore, bami fi èyí to lóore pupo ju èyí to na lo, ki o sí ṣe ibukún Re fún".
Ekeji awon malaika náà yóò máa ṣọ pe: "Olohun bá mi ṣe ipare ati ibaje sí owo ẹni tí o ko lati ma na owo re, bá mi ko iparun ba owo tabi dukia ti o ko lati na fún awon ti o lẹ to sí"

Lára àwọn àǹfààní hadiisi naa

  1. Lileto sise adua fún ọlọre fún alekun idapada, ati pe ki won fi eyi tó lòóre ju èyí tí o na parọ fun, bẹẹni lileto si sepe le ahun fún ipare dukiya rẹ ti o fí nṣe ahun, ti o siko lati na sí bi nkan ti Ọlọhun (Allah) se ni oranyan.
  2. Adua awọn malaika fún àwọn olugbagbo ododo ti won je eniire ti won na owo pelu daada ati ibukun, ati pe adua won koni sá láì gba.
  3. Siseni lojuloyin nipa ninawo sibi nkan ti o je dandan ati awon àṣegbore; gege bi ninawo fun awon araale, ati didabipo, ati awon ojupona daada.
  4. Alaye ọlá ti nbe fún ẹni tí n nawo rẹ sí awon ojupona oloore, ati igbeyin Re Nipe Olohun yóò fi mi rọpo fún, Allah (Olohun) ti Ola Re ga jù lọ so pe: (ohun kohun ti e bá na Olohun ni yóò fi imi ropo, Oun naa ni o lóore jù lọ ní Olupese fún ni).
  5. Eleyi ni iṣẹ epe fún ẹni tí kò ṣe inawo ti o pan dandan fún, sungbon awon inawo ti kii se dandan (eyi ti a fe), ohun kò sí ni bẹ; nitoripe ẹni tí o ni inawo yi ko le to sí adura yi,
  6. Ṣíṣe ahun ati k'okogun (ahun dé orí emi araa ẹni) ni èèwò.
Ìtumọ̀ sí èdè mìíràn: Èdè Gẹ̀ẹ́sì Èdè Urdu Èdè Sípéènì Èdè Indonéṣíà Èdè Uyghur Èdè Bangali Èdè Faransé Èdè Tọ́kì Èdè Rọ́ṣíà Èdè Bosnia Èdè Sinhala Èdè India Èdè Ṣáínà Èdè Páṣíà Èdè Vietnamese Èdè Tagalog Ti Kurdish Èdè Hausa Ti Pọtuga Malayalam Èdè Telgu Ti èdè Sawahili Thai Pashto Assamese Ìtumọ̀ sí èdè Amharic Ìtumọ̀ sí èdè Dutch Titi èdè Gujarat Ti èdè ìlú Nepal Ti èdè ilu Hungary الجورجية
Ṣíṣe àfihàn àwọn ìtumọ̀ sí èdè mìíràn