عَنْ أَبِي هُرَيْرَةَ رَضِيَ اللَّهُ عَنْهُ أَنَّ النَّبِيَّ صَلَّى اللهُ عَلَيْهِ وَسَلَّمَ قَالَ:
«مَا مِنْ يَوْمٍ يُصْبِحُ العِبَادُ فِيهِ إِلَّا مَلَكَانِ يَنْزِلاَنِ، فَيَقُولُ أَحَدُهُمَا: اللَّهُمَّ أَعْطِ مُنْفِقًا خَلَفًا، وَيَقُولُ الآخَرُ: اللَّهُمَّ أَعْطِ مُمْسِكًا تَلَفًا».
[صحيح] - [متفق عليه] - [صحيح البخاري: 1442]
المزيــد ...
Lati ọdọ Abu Hurayrah, kí Ọlọhun bá wa yọnu si, o sọ pe: dájúdájú Anọbi - ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ máa ba - sọ bayi pe:
Kosi ọjọ kan ti awọn ẹrusin yóò jí ní àárọ̀ ayaafi kí ó jasipe awọn malaika (iranṣẹ Ọlọhun) meji yoo sọkalẹ sí ọdọ ẹnikọọkan, ọkan ninu awọn mejeeji yóò máa ṣọ pe: "Irẹ Ọlọhun dakun bá mi ṣe iropo owo fún ẹni tí n nawo rẹ, bẹẹ ni ikeji yóò máa ṣọ pe: "Bami fi iparun ati ibajẹ sinu owo ẹni tí ó kọ̀ lati ma na owo, tí ó wowọ́ mọ́n owo kankan.
[O ni alaafia] - [Ohun ti wọ́n fi ẹnu kò lé lórí ni] - [Sọhiihu ti Bukhaariy - 1442]
Anọbi (ki ikẹ Olohun ati ola Re máa bá) ti fún wa ni iro pe kosi ojo kan ti oorun yo tabi ayaafi ki awon malaika meji sokale ti won yóò sì máa pe Olohun, okan ninu won yóò sọ pé:
"Olohun bami fi ọpọ ropo fún ẹni tí n nawo rẹ ni itẹle aṣẹ Olohun, ati fún awon ebi (ọmọ, iyawo, baba, ati iya....) ati igbalejo, ati sí bí awon iṣẹ àṣegbore, bami fi èyí to lóore pupo ju èyí to na lo, ki o sí ṣe ibukún Re fún".
Ekeji awon malaika náà yóò máa ṣọ pe: "Olohun bá mi ṣe ipare ati ibaje sí owo ẹni tí o ko lati ma na owo re, bá mi ko iparun ba owo tabi dukia ti o ko lati na fún awon ti o lẹ to sí"