+ -

عَنِ ‌ابْنِ أَبِي أَوْفَى رضي الله عنه قَالَ:
كَانَ رَسُولُ اللهِ صَلَّى اللهُ عَلَيْهِ وَسَلَّمَ إِذَا رَفَعَ ظَهْرَهُ مِنَ الرُّكُوعِ قَالَ: «سَمِعَ اللهُ لِمَنْ حَمِدَهُ، اللَّهُمَّ رَبَّنَا لَكَ الْحَمْدُ، مِلْءَ السَّمَاوَاتِ وَمِلْءَ الْأَرْضِ وَمِلْءَ مَا شِئْتَ مِنْ شَيْءٍ بَعْدُ».

[صحيح] - [رواه مسلم]
المزيــد ...

Lati ọdọ ọmọ Abu Aofaa- ki Ọlọhun yọnu si i- o sọ pe:
Ojiṣẹ Ọlọhun- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- ti o ba gbe ẹyin rẹ dide lati rukuu, o maa sọ pé: "c2">“Sami’alloohu liman hamidaHu, Allahumo Robbanaa wa laKal hamdu, milhas samoowaati wa milhal ardi wa milha maa shi-ita min shaihin bahdu”.

O ni alaafia - Muslim gba a wa

Àlàyé

Anabi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- ti o ba ti gbe ẹyin rẹ dide lati rukuu ninu irun, o maa n sọ pe: "c2">“Sami’alloohu liman hamidaHu”, o n túmọ̀ si: Dajudaju ẹni ti o ba dupẹ fun Ọlọhun- ti ọla Rẹ ga- Ọlọhun- ti ọla Rẹ ga- maa da a lohun, yio si gba ọpẹ rẹ ati ẹyin rẹ, yio si san lẹsan, lẹyin naa, o maa dupẹ fun Ọlọhun pẹlu sisọ pe: "c2">“Allahumo Robbanaa wa laKal hamdu, milhas samoowaati wa milhal ardi wa milha maa shi-ita min shaihin bahdu”, ni ọpẹ kan ti o maa kun awọn sanmọ ati awọn ilẹ ati nnkan ti o n bẹ laaarin mejeeji, ti o si n kun nnkan ti Ọlọhun ba fẹ ninu nnkan kan.

Ìtumọ̀ sí èdè mìíràn: Èdè Gẹ̀ẹ́sì Èdè Urdu Èdè Indonéṣíà Èdè Uyghur Èdè Bangali Èdè Tọ́kì Èdè Sinhala Èdè India Èdè Vietnamese Èdè Hausa Èdè Telgu Ti èdè Sawahili Burmese Thai Pashto Assamese Titi Sweden Ìtumọ̀ sí èdè Amharic Ìtumọ̀ sí èdè Dutch Titi èdè Gujarat Ti èdè Kyrgyz Ti èdè ìlú Nepal Ti èdè Lithuania Ti èdè Dari Ti èdè Somalia Ti èdè Rwanda
Ṣíṣe àfihàn àwọn ìtumọ̀ sí èdè mìíràn

Lára àwọn àǹfààní hadiisi naa

  1. Ṣíṣe alaye nnkan ti a fẹ fun olukirun lati maa sọ ti o ba gbe ori rẹ dide lati rukuu.
  2. Ṣíṣe nínà tọ̀ọ̀ ati ifarabalẹ lofin lẹyin gbigbe ori kuro ni rukuu; nitori pe ko rọrun lati maa sọ iranti yii afi ti o ba nà tọ̀ọ̀ ti o si fi ara balẹ.
  3. Wọn ṣe asikiri yii ni nǹkan ti o ba ṣẹria mu ninu gbogbo ìrun, bóyá o jẹ ọranyan ni tabi naafila.