+ -

عن قيس بن عاصم رضي الله عنه قال:
أتيتُ النبيَّ صلى الله عليه وسلم أُريدُ الإسلامَ، فأَمَرَني أن أغتَسِلَ بماءٍ وسِدرٍ.

[صحيح] - [رواه أبو داود والترمذي والنسائي]
المزيــد ...

Lati ọdọ Qays ọmọ ‘Aasim- ki Ọlọhun yọnu si i- o sọ pe:
Mo lọ ba Anabi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- pe mọ fẹ gba Isilaamu, o wa pa mi láṣẹ lati wẹ pẹlu omi ati ewe sidiru.

O ni alaafia - Abu Daud ni o gba a wa

Àlàyé

Qays ọmọ ‘Aasim wa ba Anabi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- o si fẹ gba Isilaamu, ni Anabi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- ba pa a láṣẹ lati wẹ pẹlu omi ati ewe sidiru; ki o le fi ewe rẹ mọra; ati fun nnkan ti o n bẹ fun un ninu oorun dídùn.

Ìtumọ̀ sí èdè mìíràn: Èdè Gẹ̀ẹ́sì Èdè Urdu Èdè Indonéṣíà Èdè Uyghur Èdè Bangali Èdè Tọ́kì Èdè Sinhala Èdè India Èdè Vietnamese Èdè Hausa Malayalam Èdè Telgu Ti èdè Sawahili Burmese Thai Pashto Assamese Titi Sweden Ìtumọ̀ sí èdè Amharic Ìtumọ̀ sí èdè Dutch Titi èdè Gujarat Ti èdè Kyrgyz Ti èdè ìlú Nepal Ti èdè Lithuania Ti èdè Dari Ti èdè Somalia Ti èdè Rwanda
Ṣíṣe àfihàn àwọn ìtumọ̀ sí èdè mìíràn

Lára àwọn àǹfààní hadiisi naa

  1. Ṣíṣe lofin wiwẹ alaigbagbọ nigba ti o ba fẹ wọnu Isilaamu.
  2. Iyi ti o n bẹ fun Isilaamu ati iko akolekan rẹ pẹlu ara ati ẹmi papọ.
  3. Iropọ omi pẹlu awọn nnkan ti wọn mọ ko mu u jade kuro nibi ijẹ mimọ rẹ.
  4. Awọn nnkan ti o maa n mọ nnkan ti igbalode maa dipo sidiru, gẹgẹ bii ọṣẹ ati nnkan ti o jọ ọ.