+ -

عَنِ ابْنِ عَبَّاسٍ رضي الله عنهما:
أَنَّ رَجُلًا أَتَى النَّبِيَّ صَلَّى اللهُ عَلَيْهِ وَسَلَّمَ، فَكَلَّمَهُ فِي بَعْضِ الْأَمْرِ، فَقَالَ: مَا شَاءَ اللهُ وَشِئْتَ، فَقَالَ النَّبِيُّ صَلَّى اللهُ عَلَيْهِ وَسَلَّمَ: «أَجَعَلْتَنِي لِلَّهِ عَدْلًا؟ قُلْ: مَا شَاءَ اللهُ وَحْدَهُ».

[إسناده حسن] - [رواه ابن ماجه والنسائي في الكبرى وأحمد]
المزيــد ...

Lati ọdọ Ibn Abbas, ki Ọlọhun yọnu si awọn mejeeji:
Arakunrin kan wa si ọdọ Anabi Ọlọhun -ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a-, o si ba a sọrọ nipa ọrọ kan, o sọ pe: "c2">“Ohunkohun ti Ọlọhun ba fẹ, ti iwọ anabi si fẹ. ” Nígbà náà ni Anabi, ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a, wí pé: "c2">“ṣé iwọ o fi mí ṣe bakannaa pẹlu Ọlọ́run ni? Sọ pé: Ohunkóhun tí Ọlọ́run nìkan ṣoṣo bá fẹ́”
.
Isnaadu rẹ daa - Ahmad ni o gba a wa

Àlàyé

Arakunrin kan wa si ọdọ Anabi, o si ba a sọro nipa ọrọ ara rẹ, lẹ́yìn naa o sọ pe: "c2">“Ohunkohun ti Ọlọhun ba fẹ ati ohunkohun ti o ba fẹ”, Ojiṣẹ Ọlọhun, ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a, bá tako ọrọ yii o si sọ fun un pe sise idapọ fifẹ ẹda pẹ̀lú fifẹ Ọlohun pẹlu lẹ́tà "c2">“waw” jẹ ìsẹbọ kekere si Ọlọhun, ko si lẹtọọ fun Musulumi lati sọ ọ, Lẹ́yìn náà, ó ṣamọ̀nà rẹ̀ sí ọ̀rọ̀ òtítọ́ náà pé: "c2">“Ohunkóhun tí Ọlọ́hun nìkan ṣoṣo ba fẹ́,” nítorí náà ó maa ya Ọlọ́hun sọ́tọ̀ nínú ìfẹ́ Rẹ̀, kò sì nii so fifẹ ẹni kankan mọ ọn pẹlu èyíkéyìí ninu iran asopọ.

Ìtumọ̀ sí èdè mìíràn: Èdè Gẹ̀ẹ́sì Èdè Urdu Èdè Sípéènì Èdè Indonéṣíà Èdè Uyghur Èdè Bangali Èdè Faransé Èdè Tọ́kì Èdè Rọ́ṣíà Èdè Bosnia Èdè Sinhala Èdè India Èdè Ṣáínà Èdè Páṣíà Èdè Vietnamese Èdè Tagalog Ti Kurdish Èdè Hausa Ti Pọtuga Ti èdè Sawahili Pashto Assamese Titi Sweden Ìtumọ̀ sí èdè Amharic Titi èdè Gujarat Ti èdè Kyrgyz Ti èdè ìlú Nepal Ti èdè Dari Ti èdè Somalia
Ṣíṣe àfihàn àwọn ìtumọ̀ sí èdè mìíràn

Lára àwọn àǹfààní hadiisi naa

  1. O jẹ ewọ lati sọ pe: “Ohun ti Ọlọhun fẹ ati ohun ti ìwọ naa ba fẹ,” ati ohun ti o jọ ọ ninu nnkan ti asopọ fifẹ ẹru mọ fifẹ ti Ọlọhun n bẹ nibẹ pẹlu lẹ́tà WAW; torí pé ẹbọ kekere ni.
  2. Ijẹ ọranyan kikọ ohun burúkú.
  3. Ojiṣẹ Ọlọhun, ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a – daabo bo ọgbà taohid, o si di àwọn ọ̀nà ẹbọ.
  4. Nigba ti a ba n kọ aburu, o dara ki a dari ẹni ti a n pe si ibomiran ti o yẹ to si tọ́ lati fi kọ́ṣe Anọbi- ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a -.
  5. Idapọ laaarin ọrọ rẹ- ki ikẹ ati ọla Ọlọhun o maa ba a- ninu Hadiisi yii: “Ohunkohun ti Ọlọhun nikan ṣoṣo ba fẹ” ati ọrọ rẹ ninu Hadiisi miiran: “ Sọ pe: “Ohunkohun ti Ọlọhun ba fẹ, lẹyin naa ohunkóhun tí ìwọ naa ba fẹ", ni pe o ni ẹ̀tọ́ ki èèyàn sọ pe: "Ohunkohun ti Ọlọhun ba fẹ, lẹyin naa ohunkóhun tí ìwọ naa ba fẹ", ṣùgbọ́n èyí tí ó ni ọlá jù ni gbólóhùn: "Ohunkohun ti Ọlọhun nikan ba fẹ".
  6. O lẹtọọ lati sọ pe: “Ohunkohun ti Ọlọhun ba fẹ, lẹyin naa ohunkóhun tí o ba fẹ,” ṣugbọn o dara julọ lati sọ pe: “Ohunkohun ti Ọlọhun nikan ba fẹ”.