+ -

عَنِ الْبَرَاءِ رضي الله عنه:
عَنِ النَّبِيِّ صَلَّى اللهُ عَلَيْهِ وَسَلَّمَ أَنَّهُ قَالَ فِي الْأَنْصَارِ: «لَا يُحِبُّهُمْ إِلَّا مُؤْمِنٌ، وَلَا يُبْغِضُهُمْ إِلَّا مُنَافِقٌ، مَنْ أَحَبَّهُمْ أَحَبَّهُ اللهُ وَمَنْ أَبْغَضَهُمْ أَبْغَضَهُ اللهُ».

[صحيح] - [متفق عليه]
المزيــد ...

Lati ọdọ Al-Barrohu- ki Ọlọhun yọnu si i-:
Lati ọdọ Anabi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- dajudaju o sọ nipa awọn Ansar pe: "Ẹnikan ko nii nífẹ̀ẹ́ wọn afi olugbagbọ, ẹnikan ko si nii korira wọn afi sobẹ-ṣelu, ẹni ti o ba nífẹ̀ẹ́ wọn, Ọlọhun maa nifẹẹ rẹ, ẹni ti o ba si korira wọn Ọlọhun maa korira rẹ".

O ni alaafia - Ohun ti wọ́n fi ẹnu kò lé lórí ni

Àlàyé

Anabi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- sọ pe dajudaju nini ifẹ awọn Ansar ninu awọn ara Madina, jẹ àmì lori pipe igbagbọ; eleyii rí bẹ́ẹ̀ nitori gbigba iwaju wọn nibi aranṣe Isilaamu ati Anabi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a-, ati gbigbiyanju nibi gbigba awọn Musulumi sile, ati nina awọn dukia wọn ati ẹmi wọn si oju ọna Ọlọhun, ati pe kikorira wọn jẹ ami lori ṣiṣe sobẹ-ṣelu. Lẹyin naa, Anabi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- ṣàlàyé pe dajudaju ẹni ti o ba nífẹ̀ẹ́ awọn Ansar, Ọlọhun maa nifẹẹ rẹ, ẹni ti o ba si korira wọn Ọlọhun maa korira rẹ.

Ìtumọ̀ sí èdè mìíràn: Èdè Gẹ̀ẹ́sì Èdè Urdu Èdè Sípéènì Èdè Indonéṣíà Èdè Uyghur Èdè Bangali Èdè Faransé Èdè Tọ́kì Èdè Rọ́ṣíà Èdè Bosnia Èdè Sinhala Èdè India Èdè Ṣáínà Èdè Páṣíà Èdè Vietnamese Èdè Tagalog Ti Kurdish Èdè Hausa Ti Pọtuga Ti èdè Sawahili Pashto Assamese Titi Sweden Ìtumọ̀ sí èdè Amharic Titi èdè Gujarat Ti èdè Kyrgyz Ti èdè ìlú Nepal Ti èdè Dari Ti èdè Somalia
Ṣíṣe àfihàn àwọn ìtumọ̀ sí èdè mìíràn

Lára àwọn àǹfààní hadiisi naa

  1. Iṣẹ rere ti o tobi fun awọn Ansar n bẹ nibẹ, ati pe nini ifẹ wọn jẹ ami lori igbagbọ ati bibọra kuro nibi ṣiṣe sobẹ-ṣelu.
  2. Nini ifẹ awọn ayo Ọlọhun ati riran wọn lọwọ jẹ okunfa ifẹ ọlọhun fun ẹru.
  3. Ọla ti o n bẹ fun àwọn ẹni ìṣáájú akọkọ ninu Isilaamu.