عن أبي موسى رضي الله عنه أن النبي صلى الله عليه وسلم قال:
«لا نِكَاحَ إِلّا بِوَليٍّ».

[صحيح] - [رواه أبو داود والترمذي وابن ماجه وأحمد] - [سنن أبي داود: 2085]
المزيــد ...

Lati ọdọ Abu Musa- ki Ọlọhun yọnu si i- dajudaju Anabi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- sọ pé:
“Ko si igbeyawo kan afi pẹlu alaṣẹ obinrin”.

[O ni alaafia] - [Abu Daud ati Tirmiziy ati Ibnu Maajah ati Ahmad ni wọ́n gba a wa] - [Sunanu ti Abu Daud - 2085]

Àlàyé

Anabi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- n ṣàlàyé pe dajudaju obìnrin, fifẹ rẹ ko lẹtọọ afi pẹlu alaṣẹ ti yoo ta koko igbeyawo náà.

Lára àwọn àǹfààní hadiisi naa

  1. Alaṣẹ obinrin jẹ majẹmu nibi nini alaafia igbeyawo, ti o ba waye laisi alaṣẹ obìnrin, tabi ti obìnrin ba fi ara rẹ lọkọ, igbeyawo naa ko ni alaafia.
  2. Alaṣẹ obinrin ni ẹni ti o sunmọ obinrin julọ ninu awọn ọkunrin, nitori naa alaṣẹ obinrin ti o jina ko lee fi i lọkọ pẹlu bibẹ alaṣẹ obinrin ti o sunmọ.
  3. Wọn ṣe ni majẹmu nibi alaṣẹ obinrin: Ijẹ ẹni tí o ti bàlágà, ati ijẹ ọkùnrin, ati imọna nibi mimọ awọn anfaani ìgbéyàwó, ki ẹsin alaṣẹ ati obìnrin jẹ bákannáà, ẹni ti ko ba ni awọn iroyin yii lara ko lẹtọọ si ijẹ alaṣẹ obinrin nibi tita koko igbeyawo.
Ṣíṣe àfihàn àwọn ìtumọ̀ sí èdè mìíràn
Èdè: Èdè Gẹ̀ẹ́sì Èdè Urdu Èdè Sípéènì Àlékún (58)