عَنْ حَكِيمِ بْنِ حِزَامٍ رَضِيَ اللَّهُ عَنْهُ، قَالَ:
قُلْتُ: يَا رَسُولَ اللَّهِ، أَرَأَيْتَ أَشْيَاءَ كُنْتُ أَتَحَنَّثُ بِهَا فِي الجَاهِلِيَّةِ مِنْ صَدَقَةٍ أَوْ عَتَاقَةٍ، وَصِلَةِ رَحِمٍ، فَهَلْ فِيهَا مِنْ أَجْرٍ؟ فَقَالَ النَّبِيُّ صَلَّى اللهُ عَلَيْهِ وَسَلَّمَ: «أَسْلَمْتَ عَلَى مَا سَلَفَ مِنْ خَيْرٍ».

[صحيح] - [متفق عليه] - [صحيح البخاري: 1436]
المزيــد ...

Lati ọdọ Hakeem ọmọ Hizaam- ki Ọlọhun yọnu si i-, o sọ pe:
Mo sọ pé: Irẹ Òjíṣẹ́ Ọlọhun, fun mi ni iro nipa nnkan ti mo maa n se wọn ni asiko aimọkan bii saara ṣíṣe ati bibọkun kúrò lọrun ẹru ati dida ibi pọ, njẹ ẹsan wa nibẹ? Anabi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- sọ pé: “O gba Isilaamu lori nnkan ti o ṣáájú ninu daadaa”.

[O ni alaafia] - [Ohun ti wọ́n fi ẹnu kò lé lórí ni] - [Sọhiihu ti Bukhaariy - 1436]

Àlàyé

Anabi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- n ṣàlàyé pe alaigbagbọ ti o ba gba Isilaamu wọn maa san an lẹsan lori nnkan ti o n ṣe ni asiko aimọkan ṣíwájú gbigba Isilaamu rẹ ninu awọn iṣẹ oloore bii saara ṣíṣe ati bibọkun kúrò lọrun ẹru tabi siso ibi papọ.

Lára àwọn àǹfààní hadiisi naa

  1. Dajudaju awọn daadaa ti alaigbagbọ ba ṣe wọn ko nii san an lẹsan lori wọn ni ọrun ti o ba ku lori ṣíṣe aigbagbọ rẹ.
Ṣíṣe àfihàn àwọn ìtumọ̀ sí èdè mìíràn
Èdè: Èdè Gẹ̀ẹ́sì Èdè Urdu Èdè Sípéènì Àlékún (65)