عَنْ أَبِي الدَّرْدَاءِ رضي الله عنه أَنَّ النَّبِيَّ صَلَّى اللَّهُ عَلَيْهِ وَسَلَّمَ قَالَ:
«مَا شَيْءٌ أَثْقَلُ فِي مِيزَانِ الْمُؤْمِنِ يَوْمَ القِيَامَةِ مِنْ خُلُقٍ حَسَنٍ، وَإِنَّ اللَّهَ لَيُبْغِضُ الفَاحِشَ البَذِيءَ».

[صحيح] - [رواه أبو داود والترمذي] - [سنن الترمذي: 2002]
المزيــد ...

Lati ọdọ Abu Dardā'i - ki Ọlọhun yọnu si i - dajudaju Anabi - ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a - sọ pe:
«Ko si nkankan ti o wuwo julọ ninu oṣuwọn Mumuni ni ọjọ igbedide ti o to iwa daadaa, ati pe dajudaju Ọlọhun a maa korira onibajẹ onisọkusọ».

[O ni alaafia] - [Abu Daud ati Tirmiziy ni wọn gba a wa] - [Sunanu ti Tirmidhiy - 2002]

Àlàyé

Anabi - ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a - funni niroo pe dajudaju nkan ti o wuwo julọ ninu oṣuwọn Mumuni ni ọjọ igbedide ninu awọn iṣẹ ati awọn ọrọ ni iwa daadaa, ati pe ìyẹn n bẹ pẹlu titu oju ka, ati kika ṣuta kuro, ati ṣiṣe daadaa. Ati pe Ọlọhun ti ọla Rẹ ga korira ẹni ti ko dara nibi iṣe rẹ ati ọrọ rẹ, ẹni ti maa n fi ahọn rẹ sọ ibajẹ.

Lára àwọn àǹfààní hadiisi naa

  1. Ọla ti n bẹ fun iwa daadaa; nitori pe o maa n jogun ifẹ Ọlọhun fun ẹni ti ba n ṣe e, pẹlu ifẹ awọn ẹru Rẹ, ati pe oun ni o tobi julọ ninu nkan ti wọn o wọn ni ọjọ igbedide.
Ṣíṣe àfihàn àwọn ìtumọ̀ sí èdè mìíràn
Èdè: Èdè Gẹ̀ẹ́sì Èdè Urdu Èdè Sípéènì Àlékún (54)