+ -

عَنْ ‌أَبِي هُرَيْرَةَ رضي الله عنه قَالَ: قَالَ رَسُولُ اللهِ صَلَّى اللهُ عَلَيْهِ وَسَلَّمَ:
«إِذَا وَجَدَ أَحَدُكُمْ فِي بَطْنِهِ شَيْئًا، فَأَشْكَلَ عَلَيْهِ أَخَرَجَ مِنْهُ شَيْءٌ أَمْ لَا، فَلَا يَخْرُجَنَّ مِنَ الْمَسْجِدِ حَتَّى يَسْمَعَ صَوْتًا، أَوْ يَجِدَ رِيحًا».

[صحيح] - [رواه مسلم]
المزيــد ...

Láti ọ̀dọ̀ Abu Huraira- ki Ọlọhun yọnu si i- o sọ pe: Òjíṣẹ́ Ọlọhun- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- sọ pé:
«Ti ẹnikẹni ninu yin ba ri nkankan ninu ikun rẹ, ti o wa ru u loju boya nkankan jade nibẹ tabi ko jade, ki o ma ṣe jade kuro ni masalaasi titi ti yio fi gbọ ohun, tabi ki o gbọ oorun».

O ni alaafia - Muslim gba a wa

Àlàyé

Anabi – ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a - ṣe alaye pe dajudaju ti nkankan ba n ru ninu iku ẹni ti n kirun, ti ko wa mọ boya nkan jade tabi nkankan o jade? Ko gbọdọ kuro ni ori irun, ko si gbọdọ ja a lati lọ tun aluwala ṣe, titi ti yio fi ri bibẹ ẹgbin ni aridaju eleyii ti o le ba aluwala jẹ; pẹlu pe ki o gbọ didun iso, tabi ki o gbọ oorun; tori pe dajudaju nkan ti a ti mọ amọdaju rẹ ko lee yẹ pẹlu iyemeji, ati pe oun ti mọ amọdaju imọra, ti ẹgbin si jẹ nkan ti n ṣe iyemeji ninu rẹ.

Ìtumọ̀ sí èdè mìíràn: Èdè Gẹ̀ẹ́sì Èdè Urdu Èdè Indonéṣíà Èdè Uyghur Èdè Bangali Èdè Tọ́kì Èdè Sinhala Èdè India Èdè Vietnamese Èdè Hausa Malayalam Èdè Telgu Ti èdè Sawahili Burmese Thai Pashto Assamese Titi Sweden Ìtumọ̀ sí èdè Amharic Ìtumọ̀ sí èdè Dutch Titi èdè Gujarat Ti èdè Kyrgyz Ti èdè ìlú Nepal Ti èdè Lithuania Ti èdè Dari Ti èdè Somalia Ti èdè Rwanda
Ṣíṣe àfihàn àwọn ìtumọ̀ sí èdè mìíràn

Lára àwọn àǹfààní hadiisi naa

  1. Hadīth yii ipilẹ kan ni ninu awọn ipilẹ Isilaamu, o tun jẹ òfin kan ninu awọn ofin agbọye ẹsin, oun ni pe: Dajudaju amọdaju ko lee yẹ pẹlu iyemeji, ati pe ipilẹ ni wiwa nkan ti o n bẹ lori ohun ti o n bẹ lori rẹ, titi ti nkan ti o yatọ si iyẹn fi maa daju.
  2. Iyemeji o ki n lapa nibi imọra, ati pe ẹni ti n kirun si wa lori imọra rẹ lopin igba ti ko ba tii ni amọdaju ẹgbin.