عَنْ أَبِي هُرَيْرَةَ رضي الله عنه عَنِ النَّبِيِّ صَلَّى اللهُ عَلَيْهِ وَسَلَّمَ قَالَ:
«رَغِمَ أَنْفُ، ثُمَّ رَغِمَ أَنْفُ، ثُمَّ رَغِمَ أَنْفُ»، قِيلَ: مَنْ؟ يَا رَسُولَ اللهِ قَالَ: «مَنْ أَدْرَكَ أَبَوَيْهِ عِنْدَ الْكِبَرِ، أَحَدَهُمَا أَوْ كِلَيْهِمَا فَلَمْ يَدْخُلِ الْجَنَّةَ».

[صحيح] - [رواه مسلم] - [صحيح مسلم: 2551]
المزيــد ...

Lati ọdọ Abu Huraira- ki Ọlọhun yọnu si i- lati ọdọ Anabi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- o sọ pe:
"Imu kan gbolẹ, Imu kan gbolẹ, Imu kan gbolẹ", wọn sọ pé: Tani? Irẹ ojiṣẹ Ọlọhun, o sọ pe: "Ẹni ti o ba obi rẹ mejeeji nigba ogbo, ọkan ninu awọn mejeeji tabi awọn mejeeji ti ko wa wọ alujanna".

[O ni alaafia] - [Muslim gba a wa] - [Sọhiihu ti Muslim - 2551]

Àlàyé

Anabi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- tọrọ iyẹpẹrẹ ati idojuti titi o fi da gẹgẹ bii pe o ki imu rẹ bọ inu erupẹ- o paara rẹ lẹẹmẹta- wọn wa bi i leere pé: Tani ẹni yii irẹ ojiṣẹ Ọlọhun ti o ṣepe fún?
Anabi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- sọ pé: Ẹni ti o ba awọn obi rẹ mejeeji nigba ogbo- ọkan ninu awọn mejeeji tabi awọn mejeeji-, ti wọn ko wa jẹ okunfa wiwọ alujanna rẹ; ìyẹn maa ri bẹẹ torí aiṣe daadaa si awọn mejeeji ati ṣiṣẹ awọn mejeeji.

Lára àwọn àǹfààní hadiisi naa

  1. Ijẹ dandan ṣíṣe daadaa si awọn obi mejeeji ati pe o wa ninu awọn okunfa wiwọnu alujanna, pataki julọ nígbà ogbo wọn ati lilẹ wọn.
  2. Ṣiṣẹ awọn obi mejeeji wa ninu awọn ẹṣẹ ńlá.
Ṣíṣe àfihàn àwọn ìtumọ̀ sí èdè mìíràn
Èdè: Èdè Gẹ̀ẹ́sì Èdè Urdu Èdè Sípéènì Àlékún (52)