+ -

«أَلاَ أُنَبِّئُكُمْ بِخَيْرِ أَعْمَالِكُمْ، وَأَزْكَاهَا عِنْدَ مَلِيكِكُمْ، وَأَرْفَعِهَا فِي دَرَجَاتِكُمْ* وَخَيْرٌ لَكُمْ مِنْ إِنْفَاقِ الذَّهَبِ وَالوَرِقِ، وَخَيْرٌ لَكُمْ مِنْ أَنْ تَلْقَوْا عَدُوَّكُمْ فَتَضْرِبُوا أَعْنَاقَهُمْ وَيَضْرِبُوا أَعْنَاقَكُمْ؟» قَالُوا: بَلَى. قَالَ: «ذِكْرُ اللهِ تَعَالَى».
[صحيح] - [رواه الترمذي وأحمد وابن ماجه]
المزيــد ...

Lati ọdọ Abu Dardaa- ki Ọlọhun yọnu si i- o sọ pe: Anabi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- sọ pé:
"Ṣé ki n fun yin ni iro nipa eyi ti o daa julọ ninu awọn iṣẹ yín, ati eyi ti o mọ julọ ninu rẹ lọdọ Oluwa yin, ati eyi ti o ga julọ ninu rẹ ninu awọn ipo yin ti o si loore julọ fun yin ju nina wura ati fadaka lọ, ti o si loore julọ fun yin ju ki ẹ pade ọta yin ki ẹ si ge awọn ọrun wọn ki wọn si ge ọrun yin lọ? Wọn sọ pé: Bẹẹni. O sọ pe: "Iranti Ọlọhun- ti ọla Rẹ ga-".

O ni alaafia - Ibnu Maajah ni o gba a wa

Àlàyé

Anabi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- beere lọwọ awọn saabe rẹ pé: .
Njẹ ẹ fẹ ki n fun yin ni iro ki n si kọ yin ni eyi ti o daa julọ ninu awọn iṣẹ yin ati eyi ti o niyi julọ ninu rẹ ati eyi ti o ga julọ ninu rẹ ati eyi ti o mọ julọ ninu rẹ lọdọ Ọlọhun Ọba Olukapa- Alagbara ti O gbọnngbọn-? .
Ti o ga julọ ninu rẹ ninu awọn ipò yin ninu alujanna?
Ti o loore julọ fun yin ju ṣíṣe saara pẹlu wura ati fadaka lọ?
Ati eyi ti o daa julọ fun yin ju ki ẹ pade ọta yin fun ogun lọ, ki ẹ si ge awọn ọrun wọn ki wọn si ge ọrun yin lọ?
Awọn saabe sọ pe: Bẹẹni a fẹ ìyẹn.
Anabi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- sọ pé: Iranti Ọlọhun- ti ọla Rẹ ga- ni gbogbo asiko ati lori gbogbo isẹsi.

Ìtumọ̀ sí èdè mìíràn: Èdè Gẹ̀ẹ́sì Èdè Urdu Èdè Sípéènì Èdè Indonéṣíà Èdè Uyghur Èdè Bangali Èdè Faransé Èdè Tọ́kì Èdè Rọ́ṣíà Èdè Bosnia Èdè Sinhala Èdè India Èdè Ṣáínà Èdè Páṣíà Èdè Vietnamese Èdè Tagalog Ti Kurdish Èdè Hausa Ti Pọtuga Ti èdè Sawahili Thai Assamese Titi Sweden Ìtumọ̀ sí èdè Amharic Ti èdè Kyrgyz Ti èdè Dari
Ṣíṣe àfihàn àwọn ìtumọ̀ sí èdè mìíràn

Lára àwọn àǹfààní hadiisi naa

  1. Dajudaju idunnimọ iranti Ọlọhun- ti ọla Rẹ ga- ni gbangba ati kọ̀rọ̀ wa ninu awọn eyi ti o tobi julọ ninu asunmọ, ati eyi ti o ṣe anfaani julọ lọdọ Ọlọhun- ti ọla Rẹ ga-.
  2. Gbogbo awọn iṣẹ wọn ṣe wọn lofin fun igbe iranti Ọlọhun- ti ọla Rẹ ga- dúró ni, Ọlọhun- ti ọla Rẹ ga- sọ pe: (Kí o sì kírun fún ìrántí Mi). Anabi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- sọ pé: Dajudaju wọn ṣe tawaaf ati sisa safa ati mariwa, ati jiju oko lofin lati fi gbe ìrántí Ọlọhun duro ni. Abu Daud ati Tirmidhi ni wọn gba a wa.
  3. Al-'Izzu ọmọ Abdus-Salaam sọ ninu tira rẹ ti o n jẹ AL-QAWAA’ID pé: Hadiisi yii wa ninu nnkan ti o tọka si pe ẹsan ko da lori odiwọn wahala nibi gbogbo awọn ijọsin, bi ko ṣe pe Ọlọhun- ti ọla Rẹ ga- le sẹsan lori iṣẹ kekere ju ńlá lọ, ẹsan maa n da lori ìyàtọ̀ ni ipo nibi iyi.
  4. Al-Manawi sọ ninu Fayd al-Qadeer pe: Wọn tumọ Hadith yii si pe iranti dara julọ fun awọn ti wọn n ba sọrọ pẹ̀lú rẹ, ti wọn ba fi ba akin èèyàn ti o maa wúlò fun Isilaamu ni oju ogun sọ̀rọ̀, wọn maa sọ fun un pe jijagun ni, tabi ọlọrọ ti owo rẹ maa ṣe anfaani fun talika, wọn maa sọ fun un pe saara ni, àti ẹni ti o ni ikapa láti ṣe hajj, wọn maa sọ fun un pe hajj ni, tabi ẹni tí o ni obi mejeeji, wọn maa sọ fún un pé ṣíṣe dáadáa si awọn mejeeji ni, pẹ̀lú rẹ ni ibaramu ṣe maa ṣẹlẹ̀ láàárín àwọn hadith oríṣiríṣi naa.
  5. Eyi ti o pe julọ ninu iranti ni èyí tí ahọn pe pẹlu ironusi i pẹlu ọkan, lẹyin naa ni eyi ti o wáyé pẹlu ọkan nìkan ṣoṣo gẹgẹ bii ìrònú, lẹyin naa ni eyi ti o waye pẹlu ahọn nikan ṣoṣo, ati pe ẹsan n bẹ nibi ọkọọkan ti Ọlọhun ba fẹ.
  6. Ki Musulumi dunni mọ awọn iranti ti wọn so pọ mọ awọn isẹsi gẹgẹ bii awọn iranti àárọ̀ ati irọlẹ, ati wiwọnu mọsalasi, ati ile ati ile ẹgbin ati jijade kuro nibẹ.... Ati eyi ti o yàtọ̀ si ìyẹn maa jẹ ki o wa ninu awọn oluranti Ọlọhun lọpọlọpọ igba.