+ -

عَنْ سُلَيْمَانَ بْنِ صُرَدٍ رضي الله عنه قَالَ:
كُنْتُ جَالِسًا مَعَ النَّبِيِّ صَلَّى اللهُ عَلَيْهِ وَسَلَّمَ وَرَجُلاَنِ يَسْتَبَّانِ، فَأَحَدُهُمَا احْمَرَّ وَجْهُهُ، وَانْتَفَخَتْ أَوْدَاجُهُ، فَقَالَ النَّبِيُّ صَلَّى اللهُ عَلَيْهِ وَسَلَّمَ: «إِنِّي لَأَعْلَمُ كَلِمَةً لَوْ قَالَهَا ذَهَبَ عَنْهُ مَا يَجِدُ، لَوْ قَالَ: أَعُوذُ بِاللَّهِ مِنَ الشَّيْطَانِ، ذَهَبَ عَنْهُ مَا يَجِدُ» فَقَالُوا لَهُ: إِنَّ النَّبِيَّ صَلَّى اللهُ عَلَيْهِ وَسَلَّمَ قَالَ: «تَعَوَّذْ بِاللَّهِ مِنَ الشَّيْطَانِ»، فَقَالَ: وَهَلْ بِي جُنُونٌ؟

[صحيح] - [متفق عليه] - [صحيح البخاري: 3282]
المزيــد ...

Lati ọdọ Sulaiman ọmọ Suradin - ki Ọlọhun yọnu si i - o sọ bayi pe:
Mo wa lori ijoko pẹlu Anọbi (ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ máa ba a) nigbati awọn arakunrin meji nbu arawọn, ojú ọkan nínú àwọn mejeeji pọ́n kankan, bẹẹni iṣan parikẹ rẹ naa ntana jade, bayi ni Anọbi (ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Re máa ba a) sọ pé: "Dajudaju ẹmi mọ gbólóhùn kan, ti o ba le wi i ni, nkan ti nbi ninu yóò sakuro lọdọ rẹ "ti o ba le sọ pé: "mo wa iṣọ lọdọ Ọlọhun nipa aburu èṣù" (Satani), ibinu ti nbi náà yóò lọ ni wọ́n bá sọ fún un pe: dajudaju Anọbi (ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a) sọ pe: "yáa wá isọra pẹlu Ọlọhun nipa èṣù" (Satani), Arakunrin náà bá dahun pe: Se weere kọlu mi ni bi?

[O ni alaafia] - [Ohun ti wọ́n fi ẹnu kò lé lórí ni] - [Sọhiihu ti Bukhaariy - 3282]

Àlàyé

Arakunrin meji njà lọdọ Anọbi (ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ máa ba a), bẹẹ ni oju ọkan ninu awọn mejeeji ti pọ́n koko, bẹẹ ni isan to yipo ọrun rẹ ti ran jáde.
Ni ojisẹ Ọlọhun (ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ máa ba a) bá sọ pé: Dajudaju emi mọ gbólóhùn kan ti ẹni to nbinu yii bá wí i, ibinu naa yóò sa kuro fun, ti o ba le sọ pé: mo sa di Ọlọhun nibi aburu èṣù (Satani) ẹni ẹkọ ẹni egbe.
Wọ́n sọ fun un pe: Dajudaju Anọbi (ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ máa ba a) sọ pe: Wá isọra pẹlu Ọlọhun nipa èṣù (Satani).
Ni o ba dahun, o ni: se were ni mi bi?! o le ro pe ẹnikan kò nii wá isọra nipa èṣù (Satani) ayáafi ẹni tí o ba ya were.

Lára àwọn àǹfààní hadiisi naa

  1. Anọbi (ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ máa ba a) nifẹ ki o máa ṣe itọsọna ati itunise nigbati o ba ti rí okunfa rẹ.
  2. Lati ọdọ èṣù (Satani) ni ibinu ti nwá.
  3. Ipani lasẹ lati wa isọra pẹlu Ọlọhun nipa èṣù (Satani) ẹni ẹkọ ẹni egbe nigbati a ba nbinu, Ọlọhun Allah ti ọla Rẹ ga julọ sọ bayi pe: (Tí ìbínú òdì kan bá sì ṣẹ́rí sínú ọkàn rẹ̀ láti ọ̀dọ̀ èṣù (Satani), fi Allāhu wá ìṣọ́rí ...) dé ìparí aayah.
  4. Isọni lára nibi imaa bu yàn ati nkan mi to tun jọ ọ gẹgẹbí epe ṣiṣẹ, ati ileni kúrò níbi awọn mejeeji, nitori pe a maa mu ibajẹ ṣẹlẹ làárin awọn ènìyàn.
  5. Mímú ọrọ ìmọràn, (ìkìlọ) lọ ba ẹni tí kò tii gbọ ọ; ki o le se anfaani pẹlu nkan to wa nibẹ, ki o si le wúlò fun un.
  6. Anọbi (ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ máa ba a) ti sọ wa lara nibi ibinu; nitoripe aa maa tini lọ síbi aburú ati isiwawu, Anọbi (ki ikẹ ati ọla Ọlọhun máa ba a) kii dede binu ayaafi ti wọ́n bá fa ọgbà Ọlọhun ya nìkan, oun náà ni ìbínú ti ó da.
  7. An-Nawawi sọ ọrọ asọle lórí ọrọ rẹ "njẹ moya were ni bi": o le tumọ sí pé ẹni tí o sọrọ jẹ ọkan ninu awọn a seyi sọun (munaafiki), tàbí kí o jẹ ọkan ninu awọn lárúbáwá oko toluko.
Ìtumọ̀ sí èdè mìíràn: Èdè Gẹ̀ẹ́sì Èdè Urdu Èdè Sípéènì Èdè Indonéṣíà Èdè Bangali Èdè Faransé Èdè Tọ́kì Èdè Rọ́ṣíà Èdè Bosnia Èdè Sinhala Èdè India Èdè Ṣáínà Èdè Páṣíà Èdè Vietnamese Èdè Tagalog Ti Kurdish Èdè Hausa Ti Pọtuga Malayalam Èdè Telgu Ti èdè Sawahili Thai Pashto Assamese Titi Sweden Ìtumọ̀ sí èdè Amharic Ìtumọ̀ sí èdè Dutch Titi èdè Gujarat Ti èdè ìlú Nepal Ti èdè Dari Ti èdè ìlú Romania Ti èdè ilu Hungary الموري Ti ede Madagascar Ti èdè Kannada الولوف Ti èdè ìlú Ukraine الجورجية المقدونية الخميرية الماراثية
Ṣíṣe àfihàn àwọn ìtumọ̀ sí èdè mìíràn