+ -

عَنْ عَبْدِ اللهِ بنِ مَسْعُودٍ رضي الله عنه قال:
قَالَ النَّبِيُّ صلى الله عليه وسلم كَلِمَةً وَقُلْتُ أُخْرَى، قَالَ النَّبِيُّ صلى الله عليه وسلم: «مَنْ مَاتَ وَهُوَ يَدْعُو مِنْ دُونِ اللهِ نِدًّا دَخَلَ النَّارَ» وَقُلْتُ أَنَا: مَنْ مَاتَ وَهُوَ لَا يَدْعُو لِلهِ نِدًّا دَخَلَ الْجَنَّةَ.

[صحيح] - [متفق عليه]
المزيــد ...

Lati ọdọ Abdullahi ọmọ Mas'ud- ki Ọlọhun yọnu si i- o sọ pé:
Anabi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- sọ ọrọ kan, emi naa sọ omiran, Anabi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- sọ pé: "Ẹni ti o ba ku ti o si n pe akẹgbẹ kan ti o yàtọ̀ si Ọlọhun, o maa wọ ina" emi naa sọ pe: Ẹni ti o ba ku, ti ko si kii n pe akẹgbẹ kan mọ Ọlọhun, o maa wọ alujanna.

O ni alaafia - Bukhaariy gba a wa

Àlàyé

Anabi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- n sọ fun wa pe dajudaju ẹni ti o ba yi nnkan kan ninu nnkan ti o jẹ dandan lati jẹ ti Ọlọhun fun ẹni ti o yàtọ̀ si I, gẹgẹ bii pipe ẹni ti o yàtọ̀ si Ọlọhun- ti ọla Rẹ ga- tabi wiwa iranlọwọ lọ sọdọ ẹni ti o yàtọ̀ si I, ti o si ku lori rẹ, dajudaju o maa wa ninu awọn ara ina. Ọmọ Mas'ud- ki Ọlọhun yọnu si i- ṣalekun pe dajudaju ẹni ti o ba ku ti ko da nnkan kan pọ mọ Ọlọhun, dajudaju ibuṣẹripadasi rẹ ni alujanna.

Ìtumọ̀ sí èdè mìíràn: Èdè Gẹ̀ẹ́sì Èdè Urdu Èdè Sípéènì Èdè Indonéṣíà Èdè Uyghur Èdè Bangali Èdè Faransé Èdè Tọ́kì Èdè Bosnia Èdè Sinhala Èdè India Èdè Ṣáínà Èdè Páṣíà Èdè Vietnamese Èdè Tagalog Ti Kurdish Èdè Hausa Ti Pọtuga Malayalam Èdè Telgu Ti èdè Sawahili Tamil Burmese Thai Ede Jamani Ará Japan Pashto Assamese Ede Alibania Titi Sweden Ìtumọ̀ sí èdè Amharic Titi èdè Gujarat Ti èdè Kyrgyz Ti èdè ìlú Nepal Ti èdè Dari Ti èdè Somalia Ti èdè Rwanda
Ṣíṣe àfihàn àwọn ìtumọ̀ sí èdè mìíràn

Lára àwọn àǹfààní hadiisi naa

  1. Adura ṣíṣe jẹ ijọsin wọn ko gbọdọ yi i afi sọ́dọ̀ Ọlọhun- ti ọla Rẹ ga-.
  2. Ọla ti o n bẹ fun imu Ọlọhun ni ọkan ṣoṣo, ati pe dajudaju ẹni ti o ba ku lori rẹ maa wọ alujanna, kódà ki wọn fi iya jẹ ẹ lori awọn ẹṣẹ rẹ kan.
  3. Aburu ti o n bẹ fun ẹbọ, ati pe dajudaju ẹni ti o ba ku lori rẹ maa wọ ina.