عَنْ أَبِي عَبْسٍ عَبْدُ الرَّحْمَنِ بْنِ جَبْرٍ رضي الله عنه أَنَّ رَسُولَ اللَّهِ صَلَّى اللهُ عَلَيْهِ وَسَلَّمَ قَالَ:
«مَا اغْبَرَّتْ قَدَمَا عَبْدٍ فِي سَبِيلِ اللَّهِ فَتَمَسَّهُ النَّارُ».

[صحيح] - [رواه البخاري] - [صحيح البخاري: 2811]
المزيــد ...

Láti ọdọ bàbá Absin Abdur-rahman ọmọ Jabr - kí Ọlọhun yọnu si - dájúdájú òjíṣẹ Ọlọhun - kí ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ máa ba a - sọ pé:
"Gigiṣẹ ẹru kan konii bu fún erukuru ni ojú ọna Ọlọhun ki iná wa jo".

[O ni alaafia] - [Bukhaariy gba a wa] - [Sọhiihu ti Bukhaariy - 2811]

Àlàyé

Òjíṣẹ Ọlọhun (kí ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ máa ba a) fún wa ní ìró idunnu pé ẹni tí eruku bá bo ẹsẹ rẹ mejeeji nígbàtí o njagun sí oju-ọna Ọlọhun pe iná kò ní jó ẹni na.

Lára àwọn àǹfààní hadiisi naa

  1. ìfunni ní ìró idunnu fún olujagun sí ojú ọna Ọlọhun pe yóò rí ìgbàlà ati àkóyọ níbi Iná.
  2. Anọbi darukọ gigisẹ mejeeji bó ti ẹ jẹ pé erukuru náà yóò kárí gbogbo ara lapapọ; nitoripé ọpọlọpọ awọn olujagun nigbà náà ni wọn nfi ẹsẹ rìn, ti gigiṣẹ wọn yóò sì kó eruku ni gbogbo iṣesí.
  3. Ibn Hajar ṣọ pe: ti o bá ṣe pé kí eruku kan gigisẹ lasan ni yóò ṣe iná leewọ fún ni, bá wo wa ni ti ẹni ti o bá ṣe akitiyan ti o tun lo igbiyanju rẹ, ti o si lo gbogbo oun tó ní nikapa.
Ṣíṣe àfihàn àwọn ìtumọ̀ sí èdè mìíràn
Èdè: Èdè Gẹ̀ẹ́sì Èdè Urdu Èdè Sípéènì Àlékún (46)