عَنِ ابْنِ عَبَّاسٍ رَضِيَ اللَّهُ عَنْهُمَا عَنِ النَّبِيِّ صَلَّى اللهُ عَلَيْهِ وَسَلَّمَ قَالَ:
«أَلْحِقُوا الفَرَائِضَ بِأَهْلِهَا، فَمَا بَقِيَ فَلِأَوْلَى رَجُلٍ ذَكَرٍ».
[صحيح] - [متفق عليه] - [صحيح البخاري: 6737]
المزيــد ...
Láti ọdọ Ibnu Abbas -kí Ọlọhun o yọnu sí awọn méjèjì- láti ọdọ Annabi -kí ikẹ Ọlọhun àti ọla Rẹ o máa ba a, o s'ọpe:
“Ẹ fi àwọn ìpín ogún (fara’id) fún àwọn tí ó tọ si, oun tí ó bá ṣẹkù lẹ́yìn náà, kó lọ fún ọkùnrin tí ó sunmọ́ (oku) jù lọ (ní ìbátan)".
[O ni alaafia] - [Ohun ti wọ́n fi ẹnu kò lé lórí ni] - [Sọhiihu ti Bukhaariy - 6737]
Annabi -kí ikẹ Ọlọhun àti ọlá Rẹ o maa ba- n paṣẹ fún àwọn tí ń ṣàkóso ogún pínpín pé kí wọ́n pín (ogun ti oku fi silẹ) fún àwọn tí ó tọ si, ni ìpín ti o ṣe dede ofin (shari'a), gẹ́gẹ́ bí Ọlọ́hun ṣe fẹ́. Nítorí náà, a máa fún àwọn onípin tí a ti sọ ìpín wọn di mímọ́ nínu tira Ọlọ́hun ní ipin wọn, tí awọn ìpín naa si jẹ: ìdáméjì ninu ida mẹta ogún, idankan idamẹta, idafa, ìdajì, idamẹrin, ati idamejọ ogún, ohun tí o ba wa sẹku lẹyin naa, a o fún ẹni tí ó sunmọ́ oku jù lọ ninu awọn ọkùnrin, ti wọ́n sì ń pè wọn ní Al-‘asabah (àwọn ìbátan ọkùnrin tí ń jogún ohun tí ó sẹkù lẹyin ti a pin ogun tan).