عن أبي صِرْمة رضي الله عنه أن رسول الله صلى الله عليه وسلم قال:
«مَنْ ضَارَّ ضَارَّ اللهُ بِهِ، وَمَنْ شَاقَّ شَقَّ اللهُ عَلَيْهِ».

[حسن] - [رواه أبو داود والترمذي وابن ماجه وأحمد] - [سنن الترمذي: 1940]
المزيــد ...

Láti ọ̀dọ̀ Abu Sirmah- ki Ọlọhun yọnu si i- pe Anọbi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- sọ pé:
“Ẹni tí ó bá kó ìpalára ba ẹlòmíràn, Ọlọhun maa ko ìpalára ba oun naa, ẹni tí ó bá ko ìnira ba ẹlòmíràn, Ọlọhun maa ko ìnira ba oun naa”.

[O daa] - [Abu Daud ati Tirmiziy ati Ibnu Maajah ati Ahmad ni wọ́n gba a wa] - [Sunanu ti Tirmidhiy - 1940]

Àlàyé

Anọbi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- ṣọ wa lara kuro nibi mimu ìpalára wọlé tọ Musulumi, tabi fifi ìnira kan an nibi èyíkéyìí àlámọ̀rí; yálà nibi ẹ̀mí rẹ ni, tabi dúkìá rẹ, tabi ará-ilé rẹ. Ẹni tí ó bá wa ṣe iyẹn, Ọlọhun maa san an ni ẹsan, O si maa fi ìyà jẹ ẹ ninu iran iṣẹ ti o ṣe.

Lára àwọn àǹfààní hadiisi naa

  1. Ṣíṣe kiko ìpalára ati ìnira ba Musulumi ni eewọ.
  2. Ọlọhun maa n ba àwọn ẹrú Rẹ gba ẹsan.
Ṣíṣe àfihàn àwọn ìtumọ̀ sí èdè mìíràn
Èdè: Èdè Gẹ̀ẹ́sì Èdè Urdu Èdè Sípéènì Àlékún (67)