«أَلاَ أُحَدِّثُكُمْ حَدِيثًا عَنِ الدَّجَّالِ، مَا حَدَّثَ بِهِ نَبِيٌّ قَوْمَهُ؟ إِنَّهُ أَعْوَرُ، وَإِنَّهُ يَجِيءُ مَعَهُ بِمِثَالِ الجَنَّةِ وَالنَّارِ،* فَالَّتِي يَقُولُ إِنَّهَا الجَنَّةُ هِيَ النَّارُ، وَإِنِّي أُنْذِرُكُمْ كَمَا أَنْذَرَ بِهِ نُوحٌ قَوْمَهُ».
[صحيح] - [متفق عليه]
المزيــد ...
Lati ọdọ Abu Huraira- ki Ọlọhun yọnu si i- o sọ pe: Ojiṣẹ Ọlọhun- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- sọ pé:
"Ṣé ki n sọ ọrọ kan fun yin nipa dajjal, ti Anabi kan ko sọ nipa rẹ ri fun ijọ rẹ? O jẹ olójú kan, o maa mu nnkan ti o da bii alujanna ati ina wa pẹlu rẹ, eyi ti o n pe ni alujanna ni ina, mo n ṣekilọ fun yin gẹgẹ bi Nuh ṣe ṣekilọ fun ijọ rẹ pẹlu rẹ".
O ni alaafia - Ohun ti wọ́n fi ẹnu kò lé lórí ni
Anabi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- n sọ fun awọn saabe rẹ nipa dajjal ati awọn iroyin rẹ ati awọn ami rẹ pẹlu nǹkan ti Anabi kan ko sọ ri ṣíwájú rẹ, ninu ìyẹn ni:
Pe o jẹ olójú kan.
Ati pe dajudaju Ọlọhun- ti ọla Rẹ ga- fi nnkan ti o daa bii alujanna ati ina pẹlu rẹ, ni ibamu si riri oju.
Ṣugbọn alujanna rẹ jẹ iná, ti ina rẹ si jẹ alujanna, ẹni ti o ba tẹle e o maa mu u wọ inu alujanna yii ninu nnkan ti awọn eniyan n ri, ṣùgbọ́n ina ti o n jóni ni, ẹni ti o ba yapa rẹ o maa mu u wọ ina ninu nnkan ti awọn eniyan n ri, ṣùgbọ́n alujanna ti o daa ni, Lẹyin naa, Anabi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- ṣekilọ fun wa kuro nibi wahala rẹ gẹgẹ bi Nuh ṣe ṣekilọ fun ijọ rẹ pẹlu rẹ.