عَنْ أَنَسِ بْنِ مَالِكٍ رضي الله عنه قَالَ: قَالَ رَسُولُ اللهِ صَلَّى اللهُ عَلَيْهِ وَسَلَّمَ:
«مَنْ عَالَ جَارِيَتَيْنِ حَتَّى تَبْلُغَا جَاءَ يَوْمَ الْقِيَامَةِ أَنَا وَهُوَ» وَضَمَّ أَصَابِعَهُ.
[صحيح] - [رواه مسلم] - [صحيح مسلم: 2631]
المزيــد ...
Lati ọdọ Anas ọmọ Maalik, ki Ọlọhun bá wa yọnu si i, o sọ bayi pe: Òjíṣẹ Ọlọhun - Ki ikẹ ati ọla Ọlọhun máa ba - sọ bayi pe:
"Ẹnikẹni ti ó bá ṣamojuto ọmọ obinrin meji tabi tí ó tọ́ wọn dagba titi ti wọ́n fi di ẹni ọkunrin, irufẹ ẹni bẹẹ yóò wá ní ọjọ igbende ti èmi rẹ̀ yóò wà papọ̀" Anọbi pa ọmọnika rẹ papọ̀ mọ́nrawọn.
[O ni alaafia] - [Muslim gba a wa] - [Sọhiihu ti Muslim - 2631]
Anọbi - ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ̀ máa bá a - jẹ kí amọn pé: ẹnikẹni ti Ọlọhun bá fun ni ọmọbirin meji tabi arabinrin meji, ti o wa mojuto itọju wọn daada pẹlu ẹkọ ati titọwọn sọna lọ sibi iṣẹ rere, ti o sì ṣọwọn lára kuro nibi aburu ati bẹẹ bẹẹ lọ titi ti wọ́n fi dagba, irufẹ ẹnibẹẹ yóò wà pẹlu Anọbi - ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ máa ba a - ní ọjọ igbende gẹgẹ bi ika ọwọ méjèjì yii, Anọbi ṣe àpèjúwe rẹ̀ pẹlu ika ilabẹ ati ika mogajuwọnlọ tí ó pa wọ́n pọ̀ mọ́nrawọn.