+ -

عَنْ عَبْدِ اللَّهِ بْنِ عَمْرِو بْنِ الْعَاصِ رضي الله عنهما قَالَ: قَالَ رَسُولُ اللَّهِ صَلَّى اللهُ عَلَيْهِ وَسَلَّمَ:
«إِنَّ الْإِيمَانَ لَيَخْلَقُ فِي جَوْفِ أَحَدِكُمْ كَمَا يَخْلَقُ الثَّوْبُ الْخَلِقُ، فَاسْأَلُوا اللَّهَ أَنْ يُجَدِّدَ الْإِيمَانَ فِي قُلُوبِكُمْ».

[صحيح] - [رواه الحاكم والطبراني]
المزيــد ...

Lati ọdọ Abdullahi ọmọ Amru ọmọ ‘Aas- ki Ọlọhun yọnu si awọn mejeeji- o sọ pe: Ojiṣẹ Ọlọhun- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- sọ pé:
"c2">“Dajudaju igbagbọ maa n gbó ninu ikun ẹni kọọkan yin gẹgẹ bí aṣọ ṣe maa n gbó, ki ẹ ya maa beere lọdọ Ọlọhun lati sọ igbagbọ di tuntun ninu awọn ọkan yin”.

O ni alaafia - [Al-Haakim]

Àlàyé

Anabi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- n sọ pe dajudaju igbagbọ maa n gbo ni ọkan Musulumi o si maa n lẹ gẹgẹ bi aṣọ tuntun ti o maa n gbo ti wọn ba ti lo o fun ìgbà pípẹ́; Ati pe ìyẹn maa n ṣẹlẹ̀ pẹlu okunfa adinku nibi ijọsin, tabi dida awọn ẹṣẹ ati titẹri sinu awọn adun. Anabi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- n tọ́ wa sọna lati maa pe Ọlọhun- ti ọla Rẹ ga- lati maa sọ igbagbọ wa di tuntun, pẹlu ṣíṣe awọn ọran-anyan ati pipọ ni iranti ati wiwa aforijin.

Ìtumọ̀ sí èdè mìíràn: Èdè Gẹ̀ẹ́sì Èdè Urdu Èdè Sípéènì Èdè Indonéṣíà Èdè Uyghur Èdè Bangali Èdè Tọ́kì Èdè Rọ́ṣíà Èdè Bosnia Èdè Sinhala Èdè India Èdè Vietnamese Èdè Hausa Malayalam Èdè Telgu Ti èdè Sawahili Burmese Thai Pashto Assamese Ede Alibania Titi Sweden Ìtumọ̀ sí èdè Amharic Ìtumọ̀ sí èdè Dutch Titi èdè Gujarat Ti èdè Kyrgyz Ti èdè ìlú Nepal Ti èdè Lithuania Ti èdè Dari Ti èdè ìlú Serbia Ti èdè Somalia Ti èdè ìlú Tajikistan Ti èdè Rwanda
Ṣíṣe àfihàn àwọn ìtumọ̀ sí èdè mìíràn

Lára àwọn àǹfààní hadiisi naa

  1. Ṣíṣenilojukokoro lori bibeere ìdúróṣinṣin ati sisọ igbagbọ di tuntun ninu ọkan lọdọ Ọlọhun.
  2. Igbagbọ jẹ ọrọ ati iṣẹ ati adisọkan, o maa n lekun pẹlu itẹle, ó si maa n dinku pẹlu ẹṣẹ.