+ -

عَنِ ابنِ مَسعُودٍ رَضِيَ اللَّهُ عَنْهُ قَالَ: قَالَ رَسُولُ اللهِ صَلَّى اللهُ عَلَيْهِ وَسَلَّمَ:
«لَا يَحِلُّ دَمُ امْرِئٍ مُسْلِمٍ إِلَّا بِإِحْدَى ثَلَاثٍ: الثَّيِّبُ الزَّانِي، وَالنَّفْسُ بِالنَّفْسِ، وَالتَّارِكُ لِدِينِهِ المُفَارِقُ لِلْجَمَاعَةِ».

[صحيح] - [متفق عليه] - [صحيح مسلم: 1676]
المزيــد ...

Láti ọdọ Ibnu Mas'ud kí Ọlọhun yọnu si; o s'ọpé: Òjíṣẹ́ Ọlọhun kí ikẹ àti ọla Ọlọhun máa ba a s'ọpe:
«kò lẹtọ láti ta ẹjẹ musulumi kankan silẹ ayaafi pẹlu ọkan nínú nkan mẹta: Adelebọ tàbí Abilekọ l'óbìnrin tàbí l'ọkunrin tí o ba se zina, ati ẹmi kan tí o pa ẹmi keji lai l'ẹtọ, àti ẹni tí o fi ẹṣin ṣílẹ tí o si yapa kuro ninu awujọ (awọn musulumi)".

[O ni alaafia] - [Ohun ti wọ́n fi ẹnu kò lé lórí ni] - [Sọhiihu ti Muslim - 1676]

Àlàyé

Annabi -kí ikẹ Ọlọhun àti ọlá Rẹ o máa ba a- ṣe alaye pé eewọ ni lati ta ẹjẹ musulumi silẹ, àyàfi tí o ba ṣe ọkan nínú awọn nkan mẹta (wọnyi): Alakọkọ: ẹni tí o ba ṣe àgbèrè (zina), tí o si jasi pe o ti ṣe ìgbeyàwó l'ọna tí o lalaafia, nigbanaa o tọ kí a o sọ l'oko pa (titi ti ẹmi o fi bọ lara rẹ). Ẹlẹẹkeji: ẹnikẹni ti o ba maama pa ẹmi kan (ti a se l'eewọ lati pa) laisi ẹtọ, a o pa oun naa di pẹlu awọn majẹmu (ati ofin) ti o ro papọ mọ. Ẹlẹkẹta: ẹni tí o ba yapa kúrò láàrin awujọ awọn musulumi, bóyá nipa fífi ẹṣin Islam silẹ nipasẹ (Ridda), tabi ẹni tí o nya pá l'ọtọ lai ṣe (Ridda) nipasẹ fífi apakan (ofin Islam) silẹ, gẹgẹ bi awọn obilẹjẹ ènìyàn, àti awọn adigun jàle, ati awọn olujagun nínú àwọn Khawaarij àti awọn miran.

Lára àwọn àǹfààní hadiisi naa

  1. Ṣíṣe awọn nkan mẹtẹta wọnyí l'ewọ, àti pé dájúdájú ẹnikẹni tí o ba ṣe ọkan nínú wọn yio tọsi ijiyà pipá: yálà nitori (kufuru) igbe ẹsin Islam ju silẹ, tàbí kí o jẹ fún ìbáwí (Al-Haddu); fún iran kan ninu iran eniyan meji: abilekọ tàbí adelebọ (l'ọkunrin tabi l'obirin) tí o ṣe àgbèrè (zina), ati ẹni tí o maama pa ẹmi (ti a ṣe l'ewọ lati pa).
  2. Ọranyan kí a sọ ijẹ́ ọmọluabi àti mimọ rẹ.
  3. Ọranyan bíbọwọ/iṣe apanle fún musulumi, àti pé a se ẹjẹ rẹ l'ewọ.
  4. Iṣeni ni ojúkòkòrò lórí iduró ṣinsín ninu awujọ awọn musulumi àti pe kí a má ṣe y'apa kuro ninu wọn.
  5. Dídára ìkọni lẹkọ Annabi -kí ikẹ Ọlọhun àti ọlá Rẹ o máa ba a- látara pé a máa mú ọrọ rẹ wa nigbami ni ọnà pínpín, nítorípé pínpín ọrọ (lẹka lẹka) a máa ṣe akopọ àti akotan ọrọ (imọ), a si maa yara láti ṣe e há sí ọpọlọ.
  6. Ọlọhun ṣe ìjẹni nìyà (ìbáwí) l'ofin; láti fi dẹkun awọn olu-dẹsẹ, àti láti fi dáàbò bo àwùjọ, bakannaa lati fi sọ (àwùjọ) nibi awọn iwa ọdaran.
  7. Ṣíṣe amulo awọn ìdájọ ìjẹni niyà (ìbáwí) wa ninu ojuṣe Olori ni kan.
  8. Awọn ìdí tí ofin ìpànìyàn yio fi jẹ mimulo jù mẹta lọ, ṣugbọn nwọn o leè jáde kúrò ninú awọn mẹta nwọn yii, Ibnu Al-Arabi Al-maaliki sọ pé: "wọn ko leè jáde kúrò ninú mẹtẹta nwọn yí botiwu korí: nítorípé dájúdaju ẹni tí o ba pidán tàbí o bú Annabi ti di Keferi (Alaigbagbọ), o si ko sínú ẹni tí o fi ẹṣin rẹ silẹ.
Ìtumọ̀ sí èdè mìíràn: Èdè Gẹ̀ẹ́sì Èdè Urdu Èdè Sípéènì Èdè Indonéṣíà Èdè Uyghur Èdè Bangali Èdè Faransé Èdè Tọ́kì Èdè Rọ́ṣíà Èdè Bosnia Èdè Sinhala Èdè India Èdè Ṣáínà Èdè Páṣíà Èdè Vietnamese Èdè Tagalog Ti Kurdish Èdè Hausa Ti Pọtuga Malayalam Èdè Telgu Ti èdè Sawahili Tamil Thai Ede Jamani Pashto Ede Alibania Titi èdè Gujarat Ti èdè ìlú Nepal Ti èdè Lithuania Ti èdè Dari Ti èdè ìlú Serbia Ti èdè ìlú Tajikistan Ti èdè ilu Hungary Ti èdè Czech Ti ede Madagascar Ti èdè Fulani Ti èdè Kannada Ti èdè ilu Uzbekistan Ti èdè ìlú Ukraine الجورجية المقدونية الخميرية الماراثية
Ṣíṣe àfihàn àwọn ìtumọ̀ sí èdè mìíràn
Àlékún