+ -

عَنِ النَّوَّاسِ بْنِ سِمْعَانَ الْأَنْصَارِيِّ رضي الله عنه قَالَ:
سَأَلْتُ رَسُولَ اللهِ صَلَّى اللهُ عَلَيْهِ وَسَلَّمَ عَنِ الْبِرِّ وَالْإِثْمِ، فَقَالَ: «الْبِرُّ حُسْنُ الْخُلُقِ، وَالْإِثْمُ مَا حَاكَ فِي صَدْرِكَ، وَكَرِهْتَ أَنْ يَطَّلِعَ عَلَيْهِ النَّاسُ».

[صحيح] - [رواه مسلم] - [صحيح مسلم: 2553]
المزيــد ...

Lati ọdọ An-nawwaas ọmọ Sim'aan al-ansaariy - ki Ọlọhun yọnu si i - o sọ pé:
Mo beere lọwọ Anọbi (ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ máa ba a) nípa iṣẹ daada ati iwa ẹṣẹ, lo bá sọ pé: "daada ni iwa daada, ẹṣẹ ni nkan ti nlọ ti mbọ ninu igbaaya rẹ, ti kò sì wù ọ ki awọn eniyan mọn ".

[O ni alaafia] - [Muslim gba a wa] - [Sọhiihu ti Muslim - 2553]

Àlàyé

Wọ́n bi Anọbi (ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ máa ba a) nípa iṣẹ daada ati iwa ẹṣẹ, ni o ba daun pe:
Èyí tó tóbi jù nínú iṣẹ daada ni iwa rere pẹlu Ọlọhun láti ara ìbẹrù Rẹ, ati pẹlu awọn ẹda pẹlu imaa gbé àìda mọra, ìbínú niwọnba, itujuka, ọrọ ti o da lẹnu, ida ẹbi pọ, itẹle aṣẹ Ọlọhun, iṣe pẹlẹ, iṣe daada, ibani lo lọna to da, àti ibarinpọ tó da.
Ṣugbọn ẹṣẹ oun ni nkan ti nlọ ti mbọ ninu ìgbààyà nínú àwọn iruju ati seyi sòún ọkàn láì sí isipaya igbaaya fún un, ti iyemeji nipa rẹ ati ìbẹrù nípa pe se ẹsẹ ni tabi kii se ẹsẹ ti kosi fẹ lati se afihan pe aida ni si awọn ojulowo ati awọn ti wọn pe leniyan, nitoripe adamọ ni pé ẹmi fẹ lati jẹ ki awọn ènìyàn rí daada rẹ, ti kò bá fé kí awọn eniyan ri awọn apákan iṣẹ rẹ, a jasipe iṣẹ naa kosi oore níbẹ.

Lára àwọn àǹfààní hadiisi naa

  1. iṣeni lojúkòkòrò lórí awọn iwa apọnle, nítorípé ìwà daada wa nínú èyí tó tóbi jù nínú awọn iṣẹ daada.
  2. òdòdò ati ọrọ méjèjì o dàrú mọn olugbagbọ òdodo lójú , ko da yoö mà da odo
  3. nínú awọn àmìn ẹṣẹ ni kí ọkan máa daamu ko si má dúró loju kan, ati ko má fẹ kí àwọn ènìyàn ri i.
  4. As-sanadiy sọ pé: eleyi wà fún àwọn ọrọ tó rujupọ èyí tí awọn ènìyàn ko ni ìmọ lati mukan ninu méjèejì, ti kii bá ṣe bẹ nkan ti won pa wa laṣẹ ninu ìlànà ofin láì sí ihan ẹrí nípa rẹ yatọ sí eleyi ninu daada, ati pe eyi ti wọn kọ̀ fún wa ninu ẹṣẹ, kò sí bukata kan fún méjèejì lati máa tún bèerè idajọ rẹ lọdọ ọkan tabi iwa ifọkanbalẹ rẹ.
  5. ẹni tí wọn bá sọrọ ninu hadith náà ni awọn ti wọn ni adamọ ti o lalaafia, kii ṣe awọn ọkan ti nṣàarẹ eyi ti ko mọ daada kan bẹẹ ni ko le kọ̀ àìdá kan àyàafi eyi ti o ba ti inu ìfẹẹ inu rẹ wa.
  6. At-tiibiyy sọ pé: wọn sọ pé wọn tumọ daada ninu hadith náà si awọn ìtumọ ti o pọ, wọn tumọ rẹ ni ààyè kan sí nkan ti ẹmi balẹ le lórí ti ọkan naa si balẹ le lórí, wọn tun túmọ rẹ sí ìgbàgbọ, ni ààyè mi wọn tumọ rẹ sí nkan ti yóò mú ọ sunmọ Olúwa rẹ, nibiyi wọn tumọ rẹ sí ìwà daada, ìwà daada ni wọ́n tumọ sí ìgbé àìdá mọra àti ìbínú niwọnba ati itujuká ati ọrọ daada lẹnu, gbogbo rẹ náà ló súnmọ ara won ni itumọ.
Ìtumọ̀ sí èdè mìíràn: Èdè Gẹ̀ẹ́sì Èdè Urdu Èdè Sípéènì Èdè Indonéṣíà Èdè Bangali Èdè Faransé Èdè Tọ́kì Èdè Rọ́ṣíà Èdè Bosnia Èdè Sinhala Èdè India Èdè Ṣáínà Èdè Páṣíà Èdè Vietnamese Èdè Tagalog Ti Kurdish Èdè Hausa Ti Pọtuga Malayalam Èdè Telgu Ti èdè Sawahili Thai Pashto Assamese Titi Sweden Ìtumọ̀ sí èdè Amharic Ìtumọ̀ sí èdè Dutch Titi èdè Gujarat Ti èdè ìlú Nepal Ti èdè Lithuania Ti èdè Dari Ti èdè ìlú Romania Ti èdè ilu Hungary الموري Ti ede Madagascar Ti èdè Kannada Ti èdè ilu Uzbekistan Ti èdè ìlú Ukraine الجورجية المقدونية الخميرية الماراثية
Ṣíṣe àfihàn àwọn ìtumọ̀ sí èdè mìíràn