عَنْ عُقْبَةَ بْنِ عَامِرٍ رضي الله عنه قَالَ:
قُلْتُ: يَا رَسُولَ اللهِ مَا النَّجَاةُ؟ قَالَ: «امْلِكْ عَلَيْكَ لِسَانَكَ، وَلْيَسَعْكَ بَيْتُكَ، وَابْكِ عَلَى خَطِيئَتِكَ».
[صحيح] - [رواه الترمذي وأحمد] - [سنن الترمذي: 2406]
المزيــد ...
Lati ọdọ 'Uqbatu ọmọ 'Aamir - ki Ọlọhun yọnu si i - o sọ pé:
"Mo sọ pé: Mope irẹ ojisẹ Ọlọhun kini ìgbàlà? O sọ pé: “ko ahán rẹ ni ijanu, jẹ kí ilé rẹ gba ọ laaye, ki o si máa sunkún lori awọn àsise rẹ".
[O ni alaafia] - [Tirmiziy ati Ahmad ni wọ́n gba a wa] - [Sunanu ti Tirmidhiy - 2406]
'Uqbatu ọmọ 'Aamir ki Ọlọhun yonu si beere lọwọ Anọbi (ki ikẹ Ọlọhun ati ola Re máa bà nipa Òkùnfà ti olugbàgbọ òdodo yóò fi ri àkóyọ láyé ati lọrún?.
Ni o jisẹ Ọlọhun (ki ikẹ ati ọla Rẹ máa ba) wa sọ pé: nkán mẹta di ọwọ rẹ:
Èkíní: ṣọ ahán rẹ kúrò ní bi nkán ti kosi óòre ni bẹ, ati kúrò ní bi gbogbo ọrọ aburu, ma se sọ ọrọ kan a fi ko jẹ ọrọ dàda.
Ikeji: fìdí rẹ mọ ile re ki o lè máa ṣe ìjọsìn fún Ọlọhun ni kọkọ (nigbati o ba da wa), gbaju mọ itẹle aṣẹ Ọlọhun Ọba to gbọngbọn ti o tun ga jùlọ, dáwà ninu ile rẹ lati sa fún wà àlà .
Ikẹta: Máa sunkún ki o sí máa ṣe àbámo ki o sí tuuba (tọrọ aforinjin ati iyowọ kúrò) ni bi awon ẹsẹ ti o ti ṣe kọja.