عَنْ أَبِي هُرَيْرَةَ رضي الله عنه عَنِ النَّبِيِّ صَلَّى اللهُ عَلَيْهِ وَسَلَّمَ قَالَ:
«لَوْلَا أَنْ أَشُقَّ عَلَى الْمُؤْمِنِينَ -أَوْ: عَلَى أُمَّتِي- لَأَمَرْتُهُمْ بِالسِّوَاكِ عِنْدَ كُلِّ صَلَاةٍ».
[صحيح] - [متفق عليه] - [صحيح مسلم: 252]
المزيــد ...
Lati ọdọ Abu Hurayrah - ki Ọlọhun yọnu si i - lati ọdọ Anabi - ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a - o sọ bayi pe:
Ti ki báa ṣe pe kin má ko waala bá awọn olugbagbọ ododo ni - tabi awọn ijọ mi ni - mi o ba pa wọ́n laṣẹ lati máa rin pako ni gbogbo asiko Irun kọọkan.
[O ni alaafia] - [Ohun ti wọ́n fi ẹnu kò lé lórí ni] - [Sọhiihu ti Muslim - 252]
Annabi - ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a fún wa niro pe, ti ki baa ṣe ìbẹrù waala fún awọn olugbagbọ ododo ninu awọn ijọ rẹ̀, ko ba ṣe ni dandan fun wọn lati ma run pako ni gbogbo igba ti wọ́n ba fẹ kirun.