عَنْ أَبِي هُرَيْرَةَ رضي الله عنه عَنِ النَّبِيِّ صَلَّى اللهُ عَلَيْهِ وَسَلَّمَ قَالَ:
«لَوْلَا أَنْ أَشُقَّ عَلَى الْمُؤْمِنِينَ -أَوْ: عَلَى أُمَّتِي- لَأَمَرْتُهُمْ بِالسِّوَاكِ عِنْدَ كُلِّ صَلَاةٍ».

[صحيح] - [متفق عليه] - [صحيح مسلم: 252]
المزيــد ...

Lati ọdọ Abu Hurayrah - ki Ọlọhun yọnu si i - lati ọdọ Anabi - ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a - o sọ bayi pe:
Ti ki báa ṣe pe kin má ko waala bá awọn olugbagbọ ododo ni - tabi awọn ijọ mi ni - mi o ba pa wọ́n laṣẹ lati máa rin pako ni gbogbo asiko Irun kọọkan.

[O ni alaafia] - [Ohun ti wọ́n fi ẹnu kò lé lórí ni] - [Sọhiihu ti Muslim - 252]

Àlàyé

Annabi - ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a fún wa niro pe, ti ki baa ṣe ìbẹrù waala fún awọn olugbagbọ ododo ninu awọn ijọ rẹ̀, ko ba ṣe ni dandan fun wọn lati ma run pako ni gbogbo igba ti wọ́n ba fẹ kirun.

Lára àwọn àǹfààní hadiisi naa

  1. Aanu ati iṣepẹlẹ Anọbi - ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a - fún awọn ijọ rẹ, ati ifoya (ìbẹrù) waala (ìnira) fún àwọn ìjọ rẹ.
  2. Ìpìlẹ ni pe ti Anọbi ba paṣe - ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ máa ba a - yoo tumọn sí ọranyan (dandan) àyaàfi tí ẹrí mi ba wà ti o ntọkasi pe aṣegbọrẹ ni.
  3. Fifẹ ti a fẹ ki a run pako ati ọlá rẹ̀ ni gbogbo asiko irun.
  4. Ibn Daqeeq Al-hiid sọ bayi pe: ọgbọn ati oye ti o wa nibi fifẹ ki a run pako nigbati a ba fẹ lọ kirun, ohun ni pe wiwa ni asiko isunmọ Ọlọhun, ti nṣe idalẹjọ pé ki o jẹ iṣesi pipe ati imọtoto, lati le ṣe afihan pataki ìjọsìn.
  5. Akotan (àpapọ) hadith náà ṣe akopọ rirun pako aláawẹ kódà bi o ṣe pé lẹyin ti oorun ti kan àtàrí, gégébí irun ọsan (sùúri) ati irun irọlẹ (Asri).
Ṣíṣe àfihàn àwọn ìtumọ̀ sí èdè mìíràn
Èdè: Èdè Gẹ̀ẹ́sì Èdè Urdu Èdè Sípéènì Àlékún (47)