+ -

عَنْ أَبِي قَتَادَةَ رضي الله عنه قَالَ: قَالَ النَّبِيُّ صَلَّى اللهُ عَلَيْهِ وَسَلَّمَ:
«الرُّؤْيَا الصَّالِحَةُ مِنَ اللَّهِ، وَالحُلُمُ مِنَ الشَّيْطَانِ، فَإِذَا حَلَمَ أَحَدُكُمْ حُلُمًا يَخَافُهُ فَلْيَبْصُقْ عَنْ يَسَارِهِ، وَلْيَتَعَوَّذْ بِاللَّهِ مِنْ شَرِّهَا، فَإِنَّهَا لاَ تَضُرُّهُ».

[صحيح] - [متفق عليه] - [صحيح البخاري: 3292]
المزيــد ...

Lati ọdọ Abu Qatada - ki Ọlọhun yọnu si i - o sọ pé: Anọbi - ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ máa ba a - sọ pé:
Lati ọdọ Ọlọhun ni ala daada ti nwa, bẹẹ ni láti ọdọ èṣù (Satani) ni ala burúkú ti nwa, ti ẹnikan nínú yín bá lá ala tí o se idẹruba fun un, ki o yáa fẹ atẹgun itọ ẹnu rẹ sí apá òsì, ki o si wa isọra pẹlu Ọlọhun nibi aburú ala náà, ti o ba se bẹẹ dájúdájú ala náà kòní kó ìnira ba a".

[O ni alaafia] - [Ohun ti wọ́n fi ẹnu kò lé lórí ni] - [Sọhiihu ti Bukhaariy - 3292]

Àlàyé

Anọbi (ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ máa ba a) fún wa niro pé ala daada ti o dun ni ninu láti ojú orun lati ọdọ Ọlọhun ni ti nwa, bẹẹ ni alakala ti ko da ti o si nbani nínú jẹ, lati ọdọ èṣù ni ti nwa.
Ẹni k'ẹni ti o bá lala ri nkan ti kò wu u, ki o ya tutọ sí apá òsì rẹ, ki o si wa isọra pẹlu Ọlọhun nibi aburu ala naa, ala náà ko nii ko aburú ba nitoripe Ọlọhun ti fi gbolohun ti o sọ yẹn se okunfa àkóyọ nibi nkan ti kò fẹ ti o le t'ara ala tí o la ṣẹlẹ.

Lára àwọn àǹfààní hadiisi naa

  1. Ala ni ohun ti eni t'osun ri loju orun rẹ, ṣugbọn o wọ pọ ki wọn lo gbólóhùn (Arruyah) fún daada ti eni náà ri àti nkan rere, bẹẹni o wọ pọ ki wọn lo gbólóhùn (Al-hulum) fún aburú ati awọn nkan ti ko da ti ẹni náà ba ri, wọn si ma nlo mejeeji sí ààyè ara wọn.
  2. Ipin àlá: 1. Ala daada, ohun ni ala òtítọ àti iro ìdùnnú lati ọdọ Ọlọhun wa, ẹni tó sún aa ri fún raa rẹ tabi ki wọn la ala náà si, 2. Ọrọ ti ẹmi ba araarẹ sọ, ohun naa ni ọrọ ti eniyan ba araarẹ sọ ni feteete, 3. Ibani ninujẹ ati idẹrubani esu (satani) ati awọn idunkoko lati ọdọ rẹ ki o le ba ọmọ anabi Adamọ ninujẹ
  3. Nkan mẹta ti o jẹ abayori nkan ti wọn sọ nipa ala daada: ki o fi ẹyin fún Ọlọhun fún ala náà, ki o si funni ni iro idunu nipa rẹ, ki o si sọ ọ jade, sugbọn ki o sọ ọ fún ẹni tí nfẹran rẹ nikan, ki o ma se sọ ọ fún ẹniti ko fẹran rẹ.
  4. Nkan máàrún ni àkòrí nkán ti wọn ṣọ nipa ẹkọ tó wà fún ala burúkú: ki ẹni naa wa isora pẹlu Ọlọhun nibi aburú ala náà, ati nibi aburú èṣù (satani), ki o si tutọ alátẹgun sí apá òsì rẹ ni ẹẹmẹta ti o ba ti ji, kò si gbọdọ sọ fún ẹnikankan rárá, ti o ba ti fẹ sùn padà ki o yi ẹgbẹ ti o fi sun siwaju pada, ti o ba se eleyi ala náà kò ní ko ìnira ba.
Ìtumọ̀ sí èdè mìíràn: Èdè Gẹ̀ẹ́sì Èdè Urdu Èdè Sípéènì Èdè Indonéṣíà Èdè Uyghur Èdè Bangali Èdè Faransé Èdè Tọ́kì Èdè Rọ́ṣíà Èdè Bosnia Èdè Sinhala Èdè India Èdè Ṣáínà Èdè Páṣíà Èdè Vietnamese Èdè Tagalog Ti Kurdish Èdè Hausa Ti Pọtuga Malayalam Èdè Telgu Ti èdè Sawahili Tamil Thai Pashto Assamese Titi Sweden Ìtumọ̀ sí èdè Amharic Ìtumọ̀ sí èdè Dutch Titi èdè Gujarat Ti èdè ìlú Nepal Ti èdè Dari Ti èdè ìlú Romania Ti èdè ilu Hungary الموري Ti ede Madagascar Ti èdè Kannada الولوف Ti èdè ìlú Ukraine الجورجية المقدونية الخميرية الماراثية
Ṣíṣe àfihàn àwọn ìtumọ̀ sí èdè mìíràn