+ -

عَنِ ‌ابْنِ عَبَّاسٍ رضي الله عنهما قَالَ:
تَوَضَّأَ النَّبِيُّ صَلَّى اللهُ عَلَيْهِ وَسَلَّمَ مَرَّةً مَرَّةً.

[صحيح] - [رواه البخاري]
المزيــد ...

Lati ọdọ ọmọ Abbās – ki Ọlọhun yọnu si awọn mejeeji – o sọ pe:
Anabi – ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a - ṣe aluwala ni ẹyọkọọkan.

O ni alaafia - Bukhaariy gba a wa

Àlàyé

Anabi – ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a – jẹ ẹni ti o ṣe pe ni awọn igba miran ti o ba ṣe aluwala yio fọ oríkèé kọọkan ninu awọn oríkèé ara rẹ ni ẹẹkan, ti yio fọ oju – ninu rẹ ni yiyọ ẹnu ati fifin imu -, ati ọwọ mejeeji ati ẹsẹ mejeeji ni ẹẹkan, ati pe eleyii ni odiwọn ti o jẹ dandan.

Ìtumọ̀ sí èdè mìíràn: Èdè Gẹ̀ẹ́sì Èdè Urdu Èdè Indonéṣíà Èdè Uyghur Èdè Bangali Èdè Tọ́kì Èdè Sinhala Èdè India Èdè Vietnamese Èdè Hausa Malayalam Èdè Telgu Ti èdè Sawahili Burmese Thai Pashto Assamese Titi Sweden Ìtumọ̀ sí èdè Amharic Ìtumọ̀ sí èdè Dutch Titi èdè Gujarat Ti èdè Kyrgyz Ti èdè ìlú Nepal Ti èdè Lithuania Ti èdè Dari Ti èdè Somalia Ti èdè Rwanda
Ṣíṣe àfihàn àwọn ìtumọ̀ sí èdè mìíràn

Lára àwọn àǹfààní hadiisi naa

  1. Eyi ti o jẹ dandan nibi fifọ awọn oríkèé ara ni ifọ ẹẹkan, eyi ti o ba si lekun nkan ti wọn fẹ ni (sunnah).
  2. Ṣiṣe aluwala ni ẹyọkọọkan ni ofin ni awọn igba miran.
  3. Nnkan ti a ṣe lofin nibi pipa ori ni ẹẹkan.